Minimum wage: 30,000 Naira ni ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́ n bèèrè fún

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ẹgbẹ osisẹ lorilẹ-ede Naijiria ti kọ lati gba ẹgbẹrun lọna mẹtadinlọgbọn gẹgẹ bi gbẹndeke owo osu awọn osisẹ lorilẹ-ede Naijiria.
Akowe gbogboogbo fun ẹgbẹ osisẹ naa, Ọmọwe Peter Ozo-Eson lo fi ọrọ yii lede fun awọn oniroyin ni ọjọ Isẹgun ni Abuja to jẹ olu-ilu orilẹ-ede Naijiria.
Ozo-Eson ni ijọba apapọ ko lasẹ lati yii adehun ti igbimọ onigun mẹta gbe le Aarẹ Buhari lọwọ pe ẹgbẹrun lọna ọgbọn Naira ni awọn fẹ ma a gba gẹgẹ bi gbendeke owo osu.
Ẹgbẹ NLC wa kilọ fun ijọba apapọ pe gbogbo awọn osisẹ lorilẹ-ede Naijiria ni yoo da isẹ silẹ, ti ijọba ko ba ṣe ohun totọ lasiko.
Igbìmọ̀ májẹ̀-kó-bàjẹ́ Nàìjíríà tẹ́wọ́ gba #27, 000 owó oṣù òṣìṣẹ́
O le ni ọdun mẹwaa ti ẹkunwo owó ọya awọn oṣiṣe Naijiria ti jẹ ẹgbẹrun mejidinlogun.
Ipade awọn igbimọ ijọba apapọ pawọpọ fẹnuko pé ẹgbẹrun mẹtadinlọgbọn ni awọn yoo maa san fawọn oṣiṣe Naijiria.

Oríṣun àwòrán, @presidency
Iyẹn lẹyin ọpọlọpọ iwọde, iyanṣẹlodi fun ikilọ ati ifẹhonuhan awọn oṣiṣẹ.
Wọn ni kete ti igbimọ yii ti fẹnuko lori odiwọn iye naa ni wọn yoo gbe àbá naa ranṣẹ sawọn aṣojuṣofin lọla ki o le jẹ itẹwọgba.
Iroyin n sọ pé àwọn ẹgbẹ oṣiṣẹ ṣi n sọ pe ẹgbẹrun lọna ọgbọn naira ni awọn fẹ ko jẹ owo oṣu oṣiṣẹ to ba kere julọ.
Bayii, ti iroyin yii, jade, A ko tii mọ igbesẹ ti ẹgbẹ oṣiṣẹ fẹ gbe, boya wọn maa gba àbá ijọb apapọ wọle tabi bẹẹ kọ.
Bi ọrọ naa ba ṣe n lọ ni BBC Yoruba a maa fi too yin leti ni ikannni yii.
















