Abiola Ajimobi: Idris yóò di Aare Akogun Musulumi ìpínlẹ̀ Oyo tuntun

Oríṣun àwòrán, idris_abolaji.a.a
Inu idunu ati ayọ ni awọn mọlẹbi gomina tẹlẹ ni ipinlẹ Oyo, Abiola Ajimobi wa bayii lẹyin ti wọn gbọ pe ọmọ wọn Idris Ajimobi yoo di Aarẹ Akogun Musulumi ni ipinlẹ naa.
Gẹgẹ bii ohun ti a gbọ, ọjọ Aiku, ọjọ Kẹjọ, oṣu Karun un, ọdun 2022 yii ni ifinijoye naa yoo waye niluu Ibadan.
Imaamu agba ilu Ibadan, Sheikh AbdulGaniyy Agbotomokekere ni yoo ṣe eto ifinijioye naa fun Idris ni mọṣalaṣi apapọ ilu Ibadan to wa ni Oja'ba.
- Ọmọ ọdún mẹ́rin wa ọkọ̀ ìyá rẹ̀, o kọlu ọkọ̀ méjì míì
- Àkójọpọ̀ àwòrán ìkíni ọdún ìtùnú àwẹ̀ àwọn òṣeré tíátà Yorùbá rèé
- Ohun tí Sunday Igboho sọ rèé nígbà tí Wole Soyinka ṣàbẹ̀wò sí i ní Cotonou
- 'Iye àwọn táa rí yọ láàyè, 23, àwọn tó kú sábẹ́ ilé alájà mẹ́ta ní Ibadan, Ebute Meta jẹ́ 10'
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá fi ṣìkún òfin mú "Paracetamol" ní ìpínlẹ̀ Ogun
- Kàyéfì! Àwọ̀sánmọ̀ dédé yípadà dí àwọ̀ olómi ọsàn ní ìlú yìí, wo bó ṣe ṣàkóbá fún ìrìnà oríilẹ̀ àti òfurufú
- Kìnìhún nìkan kọ́ ló burú, àwọn ajá mẹ́wàá yìí náà kò fararọ!
- Dídi ọlọ́là nínú eré Tíátà kò jọ ọ́ fún àwa kan, ìdí rèé - Kunle Afod
- Alaafin Oyo tuntun yóò gorí ìtẹ́ láìpẹ́ - Makinde
Ipo Aarẹ Akogun Musulumi jẹ ọkan lara awọn ipo to ṣe pataki, to si niyi lawujọ awọn Musulumi, paapaa niluu Ibadan.
Ta ni Idris Ajimobi?
Idris Abolaji Ajimobi jẹ ọkan lara awọn ọmọ gomina tẹlẹ ni ipinlẹ Oyo, Abiola Ajimobi to di oloogbe bayii.
Abiola Ajimobi jade laye lọjọ karundinlọgbọn, oṣu Kẹfa, ọdun 2020, lẹni aadọrin ọdun leyin aisan ranpẹ.
Idris jẹ ẹnikan ti ko fẹran lati maa gbe ara sita lori afẹfẹ, amọ ọpọ araalu mọ nipa rẹ lẹyin to gbe ọmọ gomina ipinlẹ Kano, Umar Ganduje ni iyawo loṣu Kẹta, ọdun 2018, iyẹn Fatima Ganduje.
Tọkọ-taya naa kede igbeyawo ọhun loju opo Instagram lọdun naa lọhun ki igbeyawo naa to waye.
Gẹgẹ bii baba rẹ, oloṣelu ni Idris Ajimobi.
O si wa lara awọn to n dije du ipo ile igbimọ aṣofin ipinlẹ Oyo ninu eto idibo gbogbogbo ti yii waye lọdun 2023.














