Free Sunday Igboho: Ẹ jọ̀wọ́ ẹ bá wa gba Sunday Igboho sílẹ̀, agbẹnusọ rẹ̀ Koiki ké bòsí sí ìjọba ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì

Agbẹnusọ ajijagbara Sunday Adeyemo, ti gbogbo eniyan mọ si Sunday Igboho, Koiki ti ke gbajare pe ki ijọba orilẹede Ilẹ Gẹẹsi gba Sunday Igboho silẹ lọwọ ìjọba Naijiria ati orilẹede Benin.
O sọ eyi di mimọ ninu iwe ẹsun kan ti o kọ si ijọba orilede Gẹẹsi pe ki wọn ba orilẹede Benin sọrọ lati fi Sunday Igboho silẹ nitori kii se ọdaran.
Koiki ni lati bi oṣu marun sẹyin ti wọn ti mu sinu ahamọ lorilẹede Benin Republic wọn ko fi ẹsun kankan kan sibẹ wọn ko jẹ ki o kuro ni ahamọ.
- Ìròyìn BBC Yorùbá Márùn-ún tí ó mí ìgboro tìtì lọ́dún 2021
- Bàbá Itunu Babalola ṣàlàyé ìdí tó fi kọ èsì àyẹ̀wò òkú ọmọ rẹ̀ tí Cote d'Ivoire fi ráńṣẹ́
- Ọ̀jọ̀gbọ́n Akintoye ṣàgbékalẹ̀ ''App'' PAJAWIRI tí yóò máa tú àṣírí àwọn ajínigbé àti ọ̀daràn
- Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ mánigbàgbé tó wáyé lọdún 2021
- Bẹ́ẹ̀ bá ń lo òògùn amú ǹkan ọkùnrin lè fún ìbálòpọ̀ gbígbóná, àrùn rọpa rọsẹ̀ ń bọ̀ o! - NAFDAC
- Bíṣọ̀bù àgbà Desmond Tutu jáde láyé lẹ́ni àádọ̀rún ọdún
- 'Ẹ ṣọ́ ẹnu yín pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ nípa ọdún 2022, àwọn ọlọ́pàá kìlọ̀ fáwọn òjíṣẹ́ Ọlọ́run bí bẹ́ẹ̀ kọ́...'
Lati jẹ ki ijọba orilede Gẹẹsi gbọ nnkan ti o n ṣọ, Koiki ni oun ti kọ iwe ẹsun ransẹ si ilẹ Gẹẹsi.
Bakan naa ni o ti fi iwe ẹsun ransẹ si awọn ọmọ Naijiria lati buwọ lu iwe ẹsun naa.
Ti ẹ o ba gbagbe ijọba Orilede Benin Republic mu Sunday Adeyemo ninu osun keje ọdun 2021 lasiko ti o fẹ gba ibẹ lọ si orilẹede Germany.
Lẹyin eyi ni ijọba orilede Naijiria fẹsun kan pe ọdaran ni, eyi si lo mu ki wọn gbe e lọ si ile ẹjọ lorilẹede Benin.
Ṣugbọn titi di asiko yii, ko si ẹsun kan ni pato ti ijọba orilẹede naa ti fi kan an, bẹẹ wọn ko fi silẹ ni ahamọ ọgba ẹwọn to wa.

















