Buhari's warship lagos visit: Ìlú Eko yóò gbàlejò Àarẹ Muhammadu Buhari lónìí

Buhari

Oríṣun àwòrán, Garba Shehu

Aarẹ Muhammadu Buhari yoo gunlẹ si ipinlẹ Eko lonii, ọjọ kẹsan an, oṣu Kejila, ọdun 2021 yii lati ṣi awọn akanṣẹ iṣẹ kan.

Awọn akanṣẹ iṣẹ naa ni ọkọ oju mi ileeṣẹ awọn ọmọ ogun ori omi.

Bakan naa ni Aarẹ yoo tun yọju sibi ayẹyẹ kan ti yoo waye ni gbọgan ile itura Eko Hotels.

Tunde Rahman, to jẹ agbẹnusọ aṣaaju ẹgbẹ oṣelu APC, Bola Tinubu lo kede abẹwo naa ninu atẹjade kan.

Gẹgẹ bii ohun ti Rahman sọ, Buhari yoo yọju sibi ayẹyẹ iwe lori igbeaye alaga fidihẹ ẹgbẹ oṣelu APC, Bisi Akande, eyii ti yoo waye nile itura Eko Hotels lagbegbe Victoria Island.

Àkọlé fídíò, Davido yàtọ̀ s'àwọn ọ̀dọ́ olórin kan tó lè yẹ̀yẹ́ àgbà olórin, òun ló kọ́kọ́ ná mi ní béèlì N1M lágbo - Yinka Ayefele

Lara awọn ti yoo wa nibi ayẹyẹ naa ni gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-Olu pẹlu BolaTinubu funra rẹ.

Ẹwẹ, ileeṣẹ to n ri si eto irinna ni ipinlẹ Eko ti kede pe awọn yoo ti awọn ojun naa ka pa fun nnkan bii wakati mẹrin lasiko ti Aarẹ yoo fi wa l'Eko.

Àkọlé fídíò, KieKie

Ninu atẹjade ti ileeṣẹ naa fi sita, wọn ni awọn yoo dari irinna ọkọ lati Ahmadu Bello Way si Adeola Odeku, to fi mọ Adetokunbo Ademola lati aago mẹjọ aarọ si aago meji ọsan.

Kọmiṣona eto irinna, Federic Oladenhinde ṣalaye pe awọn yoo dari awọn ọkọ to yẹ ko gba awọn oju ọna ọhun si awọn agbegbe miran.

O fi da awọn olugbe ilu eko loju pe awọn yoo gbiyanju lati ri pe ko si sunkẹre-fakẹrẹ ọkọ lasiko abẹwo Aarẹ.

Àkọlé fídíò, FUTA First Class Twins