Sowore: Ìdí tí mi ò fi lè ṣiṣẹ́ pẹ̀lú Mogbalu

Oríṣun àwòrán, Sahara Reporters
Oludije fun ipo aarẹ labẹ aṣia ẹgbẹ oṣelu AAC, Ọmọyẹle Ṣoworẹ ba BBC sọrọ lori ìṣẹlẹ to mu Ezekwesili yọwọ ninu idije dupo aarẹ Naijiria.
Ṣoworẹ sọ fun BBC News Yoruba pe ohun to ṣẹlẹ si Oby Ezekwesili ti awọn ẹgbẹ oṣelu rẹ ACPN fi kọ ẹyin sii le ṣẹlẹ si Kingsley Moghalu ati Fela Durotoye to jẹ oludije YPP ati AAN, ṣugbọn ko le ṣẹlẹ si oun.
Alaye to ṣe ni pe, awọn oludije wọn yii darapọ mọ awọn ẹgbẹ oṣelu to ti wa nilẹ tẹlẹ ṣugbọn oun da ti oun silẹ ni tuntun ni.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:]
O ṣalaye wipe, bo tilẹ jẹ pe awọn oludije to ku ti ni awọn le ṣe atilẹyin fun oludije ti aparapọ ẹgbẹ oṣelu ba fa silẹ, oun ko ro pe iru igbesẹ yii maa waye.
Soworẹ ni idi ni wipe, Moghalu ti sọ pe ipinnu aparapọ ẹgbẹ oṣelu ti ko ba sọ oun di oludije, ko le yọri si rere. O ni nitori naa, oun yoo duro laye ara oun.
Oludije naa ni oun ko ni ibẹru pe ti oun ko ba parapọ pẹlu awọn oludije to ku, oun ko ni wọle.
O sọ fun BBC Yoruba pé, yatọ si pe ẹgbẹ oṣelu oun ni okikii laarin ọmọ Naijiria, oun ni oludije kan ṣoṣọ to ti fi ẹsẹ ba ipinlẹ marundinlogoji ninu mẹrindinlogoji to wa ni Naijiria.

















