You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Bandit killing in Sokoto: Àwọn agbébọn dáná sun èrò ọkọ̀ 42 láàyè ní ìpínlẹ̀ Sokoto
Ileeṣẹ ọlọpaa Naijiria sọ pe ko din ni arinrinajo mọkanlelogun to jona ku lasiko ti awọn agbebọn dena de ọkọ wọn nipinlẹ Sokoto.
Awọn ọmọ wẹwẹ naa wa lara awọn to ku.
Lasiko ti awọn eniyan naa n rinrinajo lati ilu Sabon Birni lọ si ilu Isa nitosi ibode orilẹ-ede Niger ni iṣẹlẹ naa waye.
Agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa, Sanusi Abubakar sọ fun BBC pe ọpọlọpọ eeyan lo tun ṣi n gba itọju nileewosan nitori ina to jo wọn.
Lara awọn to doola awọn to farapa sọ pe pupọ ninu awọn to ku lo jona kọja nkan ti eeyan le damọ.
Alẹ ọjọ Aje ni iṣẹlẹ naa waye, ṣugbọn iroyin rẹ ko tete jade sita nitori bi eto ibaraẹnisọrọ ko ṣe dara nibẹ.
- Ọwọ́ ọlọ́pàá ti tẹ awakọ̀ tírélà tó gbá akẹ́kọ̀ọ́ mérìnlá nílùú Eko
- Ramon Adedoyin t'ọ́lọ́pàá mú nítorí ikú Timothy Adegoke gba ilé ẹjọ́ lọ, ohun tílé ẹjọ́ sọ rèé...
- Ìbànújẹ dórí ẹbí Demilade kodò, ọdọ ìlú fi'binu dáná sún ilé pásítọ̀ tí wọ́n furasí lórí ìkú rẹ̀
- 'Ọmọ mi mẹ́rin, ọmọ àbúrò mi mẹ́ta ló wà lára àwọn ọmọ tí wọ́n bá òkú wọ́n nínú ọkọ̀'
- Ọgọ́ta èèyàn tí àwọn jàndùkú jí gbé nínú ìjọ Baptist ní Kaduna ti gba ìtúsílẹ̀
Botilẹ jẹ pe ko ti i si ẹni to mọ koko bi iṣẹlẹ ọhun ṣe waye, iroyin kan sọ pe awọn agbebọn naa mọọmọ dana sun ọkọ akero naa pẹlu ero ninu rẹ, ti awọn miran tun ni ibọn ti awsn agbebọn yin mọ ọkọ naa lo mu ko gbina.
Ni kete ti ọkọ naa gbina ni awọn agbebọn yii salọ lai mu ẹnikẹni.
Ileeṣẹ ọlọpaa ni iwadii ti bẹrẹ lori nkan to ṣokunfa iṣẹlẹ naa.
Iru iṣẹlẹ bayii, pe ki awọn agbebọn dana sun awọn ero ọkọ laaye ko waye ri ni agbegbe naa.