You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Niger boat: Àwọn òṣìṣẹ́ adóòlà ṣì n wá àwọn èèyàn tó rì sínú omi nínú ìjàmbá ọkọ ojú omi
Ko din ni eeyan mejidinlọgbọn ti wọn ti sin oku wọn, lẹyin ijamba ọkọ oju omi to waye ni abule kan ni ijọba ibilẹ Munya, nipinlẹ Niger.
Ajọ to n mojuto iṣẹlẹ ipajawiri ni ipinlẹ Niger, sọ pe ọjọ Satide ni iṣẹlẹ naa waye, ti wọn ko si ti i ri eeyan mẹjọ.
Alaga ajọ naa, Alhaji Ibrahim Inga Ahmed, sọ fun BBC pe eeyan bi ọgọrun ni ọkọ oju omi naa gbe lati Zumba, ṣugbọn ọkọ naa ni ijamba nigba to ku diẹ ki wọn o de ibi ti wọn n lọ.
- Báwo ni ìṣẹ̀lẹ̀ ikú Kayode Badru ṣe ṣẹlẹ̀ ní Celestial Church of Christ ni Eko? ẹ wo ohun tí a mọ̀!
- Emmanuel Abina, ọmọ Olùdarí ìjọ GOFAMINT, Elijah Abina jáde láyé lẹ́yìn ikú ìyàwó rẹ̀
- Rọ́kẹ̀ẹ̀tì China ti balẹ̀, orí omi Indian Ocean ló já sí!- Iléeṣẹ́ ìròyìn China
- À ń ṣe ìwádìí lọ́wọ́ bí ''candle'' ṣe pa Kayode Badru ní ìpínlẹ̀ Eko - Ọlọ́pàá
- Mi ò bú Baba Adeboye, mo kàn gégùn-ún fún àwọn tí kò ṣàtìlẹyìn fún Oduduwa Republic ni- Sunday Igboho
Iroyin sọ pe ọkọ oju omi naa kọlu nkan lori omi ni, ko to o doju de.
"Wọn ri eeyan mejilelọgọta doola lara awọn eero ọkọ, awọn mejidinlọgbọn ti ku, bẹẹni eeyan mẹjọ ko ti i di riri."
Alhaji Ahmed sọ pe awọn oṣiṣẹ adoola ẹmi ṣi n wa awọn to ṣe e ṣe ko rì sinu omi.
Ijamba ọkọ oju omi ko ṣẹṣẹ ma a waye ni ipinlẹ Niger.
Alhaji Ibrahim Inga Ahmed sọ pe eyi ko ṣẹyin bi awọn odò to wa ni ipinlẹ naa ṣe n kun akunfaya, nitori awọn odo adagun 'dam' to pọ ni ipinlẹ naa.