You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Offa robbery: Àwọn afurasí jẹ́wọ́ pé èèyàn mọ́kànlá làwọn yìnbọn pa
"Èèyàn mọ́kànlá ni a yìnbọn pa níbi ìdigunjalè Offa"
Awọn afurasi adigunjale ti wọn n jẹjọ lori iṣẹlẹ idigunjale ọjọ karun un oṣu kẹrin ọdun 2018 niluu Offa nipinlẹ Kwara ti sọ fún ileẹjọ giga ilu Ilorin pe eeyan mọkanla lawọn yinbọn pa lọjọ náà.
Awọn afurasi ọhun, Ayoade Akinnibosun, Ibikunle Ogunleye, Adeola Abraham, Azeez Salawu ati Niyi Ogundiran lo ti n jẹjọ lori iṣẹlẹ naa.
- Saraki pè fún ìwádìí ikú olórí ikọ̀ adigunjalè tó ṣọsẹ́ ní Offa
- Offa Bank Robbery: Àwọn ọlọ́pàá fí ìyà jẹ wá láti sọ nkan ti wọn fẹ ká sọ ni
- Ilé ẹjọ́ pàṣẹ ki wọ́n sọ́ afurasí 5 sì àhámọ́ lórí ìdigunjalè Ido-Ani
- Ẹ fura o! Nàìjíríà ń pín lọ díẹ̀ díẹ̀ rèé- Abdulsalami
- Kí ló mú kí géńdé Olorun fi àfọ́kù ìgò gé ǹkan ọmọkùnrin rẹ̀ ní Kano?
- Ìjọba Naijiria ti kùnà lórí ojúṣe rẹ̀ lóri ètò aàbò- Bode George
Fọnran to n ṣafihan ijẹwọ awọn afurasi ọhun ni ileẹjọ kọkọ fihan l'Ọjọru ki igbẹjọ to bẹrẹ.
Gbogbo awọn afurasi naa ayafi ọkan ṣoṣo lara wọn lo sọ pe awọn yinbọn pa eeyan mọkanla ti wọn lẹ oko mọ awọn.
Akinnibosun ṣalaye bi ọlọpaa ti wọn ti da duro lẹnu iṣẹ, Michael Adikwu ti sọ foun nipa idigunjale.
O ni lẹyin ti oun gba si Adikwu to ti di oloogbe bayii lẹnu ni oun naa mu eeyan mẹrin mii wọ iṣẹ ọhún.
O ni oun loun ni ọkọ meji tawọn lo ninu idigunjale ilu Offa.
- A fẹ́ kí ìjọba fòfin de àwọn darandaran tó máa ń fi ìbọn Ak47 da málúù láàrín ìlú- MURIC
- Gbenga Daniel kò ṣẹ̀ṣẹ̀ kúrò ní PDP, ó kàn fi ẹ̀ka APC kan sílẹ̀ lọ sí òmíràn ni- PDP
- Ìjì òtútù pa èèyàn 21 ní Amẹ́ríkà, ẹgbẹ̀lẹ́gbẹ̀ míràn ń dojúkọ ìṣoro àìsíná ẹ̀lẹ́ńtíríkì
- Wo iye kọ́ńdọ́mù táwọn ọmọ Nàìjíríà fi ń ṣara rindin lọ́dún
- Akẹ́kọ̀ọ́ ọmọ ọdún mẹ́rìnlá mú ìbọn ìléwọ́ lọ ilé ìwé láti yìín lu olùkọ́ tó ní kó gé irun orí rẹ̀
- Ọwọ́ pálábá Abubakar, mọ́káliíkì ségi níbi tó ti fẹ́ jí ọkọ̀ gbé l'Abuja
Akinnibosun ṣalaye pe Gomina ipinlẹ Kwara nigba naa, Abdulfatai Ahmed lo foun lọkan lara awọn ọkọ ọhun gẹgẹ bi ẹbun nitori olori kan loun jẹ lagbo oṣelu nipinlẹ naa.
"Ni ọjọ karun oṣu kẹrin ọdun 2018 ni emi at'awọn mẹrin ti mo mu wọ inu iṣẹ adigunjale gbera lati ilu Oro lọ si Ajase-Ipo nibi ti a gbe ọkọ SUV Lexus ti a wa ninu rẹ sí.
Lati ibẹ ni a ti gbe ọkọ Mercedes Benz lọ si ilu Offa, niwaju ile epo Total ni a duro sí nibi ti Adikwu ti n duro de wa," Akinnibosun ṣalaye.
O ṣalaye siwaju síi pe níbẹ ni Adikwu ti gbe baagi ti ibọn AK47 marun un wa ninu rẹ foun eleyii ti oun fun onikaluku ni tirẹ.
Akinnibosun ni Adikwu ṣọ pe oun wa lati gbẹsan bi ileeṣẹ ọlọpaa ṣe yọ oun niṣẹ, o ni ibọn AK47 mẹwaa lawọn gba lagọ ọlọpaa lasiko idigunjale Offa.
Àmọ́, adajọ Haleemah Salman sun igbẹjọ si ọjọ kẹẹdogun ati ọjọ kẹrindilogun, oṣu kẹta, ọdun 2021 fun igbẹjọ to kẹyin.
- Wo ẹ̀bùn owó tabua tí gbajúgbajà oníṣòwò kan fún bàbá "Lórí Irọ́"
- Ṣé lóòtọ́ ni omidan yìí ya wèrè ní kété tí ọ̀rẹ́kùnrin rẹ̀ ní òun fẹ́ fi ṣaya?
- Alhaja Muslimot Salami tí àwọn darandaran kọlù ní Ogun tí padà jẹ́ Olorun nípè!
- Àìṣàtìpó rí ló ń da Ejiogbe láàmú, àsìkò ìjọba tèmi ló dé- Alhaji Mukaila Auxilliary
- A kò tíì gbọ́ pé ilé ẹjọ́ wọ́gilé gbígba owó lọ́wọ́ àwọn dẹ́rẹ́bà ni ibudokọ ipinlẹ Oyo- awọn Awakọ̀
- Ìjọba Naijiria ti kùnà lórí ojúṣe rẹ̀ lóri ètò aàbò- Bode George