Ọmọkùnrin kan ṣekúpa awọn òbí rẹ nítorí pé wọ̀n sọ̀rọ̀ òdì sí Anọbi Muhammad

Àwòrán Mukaila Ahmad

Oríṣun àwòrán, POLICE JIGAWA

Arakunrin Munkaila Ahmadu, ẹni to ṣekupa awọn obi rẹ ni ìjọba ibilẹ Gagarawa ni Ipinlẹ Jigawa, ti ni oun gbe igbese naa nitori pe awọn obi oun sọrọ odi si ojisẹ Ọlọrun Anọbi Muhammad.

Ahmadu, ẹni to jẹ akọrin ati ọmọ ẹlẹyin ìjọ Tijjaniyya Islam ni awọn obi oun n bu anọbi, tí wọn si tun pe oun ni were nitori pe oun kọrin ẹsin.

Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Jigawa tí kede pe awọn ti fi paro ofin gbe arakunrin naa, ẹni to jẹ ọmọ ọdun mẹtadinlogoji.

Yatọ si awọn obi rẹ ti Ahmadu ṣekupa bakan naa lo tun ṣe eeyan meji lese lọjọbọ, ọjọ kiini oṣu kẹsan-an.

Ileeṣẹ ọlọpaa ni ọmọ odo ni Munkaila fi lu baba rẹ, Ahmed Muhammad, ẹni aadọrin ọdun to jẹ olori abule Zarada ni ijọba ibilẹ Gagarawa ati iya rẹ Ahmed Hauwa, ẹni ọgọta ọdun pa.

Awọn meji yooku ti o fi ọmọ odo ṣeleṣe ni wọn wa nile iwosan Gumel ni Ipinlẹ Jigawa, nibi ti wọn ti n gba itọju.

Nitori awọn obi mi kọ lati gba ootọ nipa Anọbi ni mo ṣe pa wọn

Skip podcast promotion and continue reading
Èyí ni ìkànnì Whatsapp wa

Àjáàbalẹ̀ ìròyìn BBC News Yorùbá lórí WhatsApp rẹ

Darapọ̀ mọ́ wa nibì

End of podcast promotion

Ninu fọran to wa lori ayelujara, Munkaila Ahmadu sọ pe "Mo ṣekupa awọn obi mi nitori wọn kuna lati gba otitọ nípa Anọbi Muhammad."

Mo ṣekúpa awọn obi mi nitori wọn sọrọ odi si Anọbi Muhammad ti ijiya ẹsẹ wọn si ni iku nitori ko si idariji fun ẹnikẹni to ba sọrọ odi sì ojisẹ Ọlọrun.

"Onkọrin iyin nipa ojisẹ ni mi, ninu ọdun mo pinnu lati ṣe fọran lori orin mi ti Ọlọrun yoo si fun mi ṣe, wọn ma tu mi silẹ nitori ayanfẹ Ọlọrun ni mi.

"Awọn obi ko nifẹ Anọbi Muhammad rara nítorí pe mo nifẹ rẹ, wọn pe ni were."

"Mo bẹ baba mi pe ko ṣe atilẹyin fun lori orin mi nitori mi ko kí n ko obinrin, ta tẹtẹ, jale tabi muti sugbọn o kọ."

"Iya mi maa n lọ kiri lati sọrọ mi laida pe ki awọn eeyan ma lemi níbi tí wọn ba ti ri mi tí n mọ kọrin fun ojiṣẹ Ọlọrun nitori pe ọlẹ ni mi.

"Mo wa ni agọ ọlọpaa nitori pe loju awọn eeyan, nnkan ti mo ṣe koda sugbọn niwaju Ọlọrun ati Anọbi, nnkan gidi ni mo se."

Ahmadu lọ jẹ baba ọmọ marun-un ni oun n ṣe akiyesi pe baba oun n ni ibaṣepọ pẹlu iyawo oun.

Kì ni Iléeṣẹ́ Ọlọ́pàá sọ̀ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà

Agbẹnusọ fun Ileeṣẹ ọlọpaa ni Ipinlẹ Jigawa, DSP Lawal Shisu Adam sọ fun BBC News pe iwadii ti bẹrẹ lati ṣe ayẹwo lori ìlera ọpọlọ Munkaila ati boya ko ki n mu Igbo.

"Lọjọ kini oṣu kẹsan ni dede ajọ mọkanla abọ ni iroyin tẹ wa pe arakunrin kan ẹni ọdun mẹtadinlogoji Munkaila Ahmadu ṣe ikọlu si awọn eeyan pẹlu ọmọ odo.

"Awọn ọlọpaa sare lọ síbi iṣẹlẹ naa, ti a sì gbe eeyan mẹrin lọ sile wosan sugbọn awọn meji jade laye nigba ti a fi ma de ile iwosan, iyẹn awọn obi arakunrin naa.

"Awọn meji yooku, Hakalima Ahmadu, aburo Munkaila ati Kaliu Bagudu, aradugbo to gbiyanju lati petu sì iṣẹlẹ naa."