African Eye: Ìwádìí BBC lórí ikú tó pa ọmọ ogun 26 ní Libya láti ipasẹ̀ Díróònù àìmọ̀dí

Àkọlé fídíò, African Eye: Ìwádìí BBC lórí ikú tó pa ọmọ ogun 26 ní Libya láti ipasẹ̀ Díróònù àìmọ̀dí

Losu kinni ọdun 2020, ado oloro lati oju ofurufu ba awọn asẹsẹ gba ọmọ ogun lorilẹede Libya, ti mẹrindinlọgbọn si dagbere faye loju ẹsẹ.

Gbogbo awọn ikọ to n taporogan ni Libya si lo sẹ pe awọn ko lọwọ ninu isẹlẹ naa, eyi to mu kawọn eeyan agbaye maa beere pe nibo ni ado oloro naa ti wa?

Ikọ Africa Eye, to maa n finmu finlẹ nileesẹ BBC wa bọ sigboro lati sawari ohun to fa isẹlẹ naa, ti wọn si ri pe awọn orilẹede alagbara aye ko lo baalu fi jagun mọ.

Ohun ti wọn n lo bayii ni baalu kekere kan ti wọn n pe ni diroonu lati maa fi ransẹ ogun sira wọn yika agbaye.

Iwadii ikọ Africa Eye, ninu fidio yii, si fidi rẹ mulẹ pe, orilẹede United Arab Emirate UAE ati Egypt si lo wa nidi aifararọ̀ ilẹ Libya, bi o tilẹ jẹ pe wọn tọwọ bọ iwe adehun fun ajọ isọkan orilẹede agbaye pe awọn yoo jẹ ki ogun simi ni Libya.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Bakan naa ni iwadii naa ni UAE lo lo Diroonu fi yin ado oloro to pa awọn ọmọ ogun mẹrindinlogun ni Libya losu kinni ọdun 2020.