BBC Africa Eye: O yẹ kí ìjọba ló ìmọ̀ ẹ̀rọ ìwádìí sátáláìtì láti mú àwọn Boko Haram

Awọn ọmọ Naijiria ti n sọ ero ọkan wọn nipa fidio iwaadi bi awọn agbofinro ṣe n fi iya jẹ awọn afunrasi eleyi ti BBC Africa Eye gbe jade.
Loju opo Facebook ileeṣẹ BBC Yoruba, niṣe ni awọn eeyan bu ẹnu atẹ lu bi awọn agbofinro wọnyi ko ṣe bọwọ fun ofin.
Bawọn kan ṣe n sọ pe ki ijọba kasẹ awọn SARS kuro nilẹ lawọn miiran n sọ pe ki BBC ṣe idayatọ awọn afunrasi ati awọn ti ko mọwọ mẹsẹ ninu iwaadi wọn.
- BBC tún gbé e dé! Wọ́n tú àṣírí ìfiyàjẹni àwọn Ológun àti SARS káàkiri Nàìjíríà
- Àwọn ǹkan ti ọ̀pọ̀ ko mọ nípa Baba Suwe
- Ohun tí a mọ̀ nípa ààrùn tó ń pani ní Nàìjíríà tí kìí ṣe CoronaVirus, Lassa, tàbí Ebola rèé
- Obìnrin tó rè kọjá lójú pópó ló fà ìjàmbá ọkọ́ Osun
- China ṣe àgbéjáde "App" tí ẹ lè fi mọ̀ bóyá ẹ súnmọ́ aláàrùn Coronavirus
Bẹẹ lawọn miran n beere pe kilode ti ijọba ko ṣe le fi iru ẹrọ iwaadi satalaiti ti wọn lo ninu iwaadi yi lati fi mu awọn ikọ Boko Haram.
Showemimo Victor ti o beere ọrọ yi sọ ọ ni ede Gẹẹsi.

Ninu esi tirẹ, Micheal Alloh naa fẹ ki wọn lo iru imọ yii lati tọ pinpin awọn to jẹ alajẹbanu oloṣelu.

Ni akotan pupọ awọn to ka nipa iroyin naa loju opo BBC lo kan sara si ileeṣẹ iroyin naa ti wọn si ni awọn ni ireti pe ijọba yoo wa nkan ṣe si ọrọ awọn agbofinro to n fi iya jẹ awọn afunrasi.








