Lassa Fever: Àjèjì ààrùn tó ń pani ní Nàìjíríà bàyìí kìí ṣe CoronaVirus, Lassa, tàbí Ebola

Oríṣun àwòrán, Ncdc
Ajọ to n mojuto igbogun ti aarun ni Naijiria, Nigeria Centre for Disease Control (NCDC) sọ pe ohun ti mu erooja lara omi odo ti aisan ajeji kan ti pa awọn eniyan ti ko din ni mẹẹdogun ni ipinlẹ Benue.
Ileeṣẹ eto ilera ipinlẹ Benue sọ pe awọn ti aarun naa fi ọwọ ba julọ n gbe ni ijọba ibilẹ Oye-Obi nipinlẹ naa.
Iku eniyan mẹẹdogun lo ti wa ni akọsilẹ bayii, ti ọgọrun ati mẹrin eniyan si tun ti kagbako aarun naa to bujade lọjọ kọkandinlọgbọn, oṣu Kinni, ọdun 2020.
Nkan to ba ni lẹru ni pe ajeji aarun naa tete n ran kiri ju iba Lassa to ti pa eniyan mẹtadinlaadọta lọdun 2020 nikan lọ.
- Yàtọ̀ f'àwọn mẹ́fà tó m bọ̀ láti ìpàgọ̀ àdúrà tó kú, àjọ FRSC Osun sọ ipò táwọn tó fara pa wà báyìí
- 'Kìí ṣe 'ibà Lassa' ló padà wọ ìpínlẹ̀ Benue', mọ̀ nípa ààrùn tó ti pa èèyàn 15 ní Benue
- Ọwọ́ ọlọ́pàá Eko tẹ ọmọ ọdún 22 tó jẹ́ olórí 'bambam' f'ẹ́gbẹ́ òkùnkùn Berry Boys
- Àrá sán pa aboyún ìnàkí àtàwọn mẹ́ta míì tó jẹ́ àrà ọ̀tọ̀ láyé
- Èèyàn mẹ́fá tó m bọ̀ láti ìpàgọ́ àdúrà kú nínú ìjàmbá ọkọ̀ ojú pópó l'Osun
Ni bayii, awọn alaṣẹ ipinlẹ Benue ti di ọna to lọ si odo naa pa.
Bakan naa ni ajọ NCDC ti sọ pe aarun naa kii ṣe Corona virus, iba Lassa tabi Ebola, nitori pe awọn apẹẹrẹ ti awọn to ni i fihan yatọ.
Awọn onimọ ilera sọ pe o maa n to wakati mejidinlaadọta ki esi ayẹwo to jade.
Minisita fun eto ilera ni Naijiria, Dokita Osagie Ehanire sọ pe awọn onimọ ti n wadii iru aarun to jẹ, ti wọn si n duro de e esi ayẹwo.

Oríṣun àwòrán, TWITTER/@FMOHNIGERIA
Minisita fun eto ilera sọ fun awọn akọroyin l'ọjọ Ẹti to kọja pe awọn koko to ti farahan nipa ajeji aarun naa ni pe:
- Aarun naa ti pa eniyan ti ko din ni mẹẹdogun, awọn to le ni ọgọrun lo si ni i.
- Aarun naa maa n mu ki inu ati ẹsẹ ẹni to ba ni ko wu gbẹndu
- Ijọba n fura pe o ṣeeṣe ko jẹ kẹmika ti wọn fi n pa ẹja lo n fa aarun naa
- Ajọ NCDC ti ran ikọ adoola si ipinlẹ Benue lati mu eroja fun ayẹwo lara omi odo naa












