Nigerian army: Agbésùmọ̀mí 13,000 ló jọ̀wọ́ ara wọn fún ìjọba láàrín ọ̀sẹ̀ méjí

Oríṣun àwòrán, HQ Nigerian Army
Ileeṣẹ ọmọ ogun Naijiria ti sọ pe ko din ni ẹgbẹrun mẹtala ọmọ ẹgbẹ agbesumọmi to ti jọwọ ara wọn fun ijọba apapọ laarin ọsẹ meji sẹyin.
Aṣoju alukoro ileeṣẹ ọmọ ogun, Bernard Onyeuko lo fi ọrọ naa lede nibi to ti sọ pe awọn mọlẹbi awọn agbesunmọmi naa wa lara awọn eeyan ọhun, to fi mọ awọn iyawo atawọ ọmọ wọn.
O ni awọn ṣekupa mọkandinlọgbọn lara awọn agbesumọmi naa, nigba ti wọn fi ṣikun ofin mu mẹtala ninu wọn.
- "Á fimú Odunlade Adekola dánrin tó bá kọ̀ láti ṣe àtúnṣe lórí títàbùkù ẹ̀sìn Islam nínú fíìmù rẹ̀"
- Ọ̀lọ́pàá 34,587 níjọba àpapọ̀ ń rán lọ Anambra láti kojú agbébọn tó bá gbémú
- Wo aṣòfin àpapọ̀ tó fẹ́ káwọn káfíńtà àti dẹ́rẹ́ba ọlọ́kọ̀ èrò má san owó orí, Ó ní owó kékéré kó ni wọ́n rí
- Buhari, wá nǹkan ṣe sí àwọn agbésùmọ̀mí àti agbébọn tó ń pẹ̀ka bí ìrókò-Afenifere
- Iyorchia Ayu di alága tuntun fún ẹgbẹ́ òṣèlú PDP
- A pinu láti sinmi díẹ̀ lẹ́yìn ìgbeyàwó ká tó bímọ àmọ́ ó yíwọ́ - Wumi Toriola
- Wo bí àṣà ìbálé lálẹ́ ìgbeyàwó ṣe ń dọdẹ àwọn obìnrin òde òní kiri
- Àgùnbánirọ̀ yóò kojú Boko Haram, agbébọn pẹ̀lú ìdánilẹ́kọ̀ọ́ ológun - Fayemi
Onyeuko ni "Akitiyan awọn ọmọ ogun ori ilẹ ati oju ofurufu ni iha Ariwa ila-oorun Naijiria ti so eso rere, adinkun si ti ba bi awọn agbesunmọ ni ṣe n kọlu awọn Naijiria."
"Laarin asiko ti a n sọrọ rẹ yii, pupọ ninu awọn agbesumọmi naa ni a ti ran lọ si ọrun aremabọ, ti a si ti fi ṣikun ofin mu ọpọ, to fi mo awọn to n ṣe agbodega fun wọn."
Ileeṣẹ ọmọ ogun sọ siwaju si pe eredi ree ti ọpọ ninu awọn eeyan ọhun ṣe n jọwọ ara wọn fun ijọba apapọ.
O ni "Eyi lo fa ti wọn fi jọwọ ara wọn fun ijọba ti wọn si n ko awọn ohun ija wọn silẹ tawọn ti ẹbi wọn lẹyin ti wọn ri pe ija naa kii ṣe eyii ti wọn le bori.
Lẹyin naa lo ke si awọn ọmọ Naijiria lati ṣatilẹyin fun ileeṣẹ ọmọ ogun ki ọrọ igbesumọmi le di ohun igbagbe ni Naijiria.













