Insecurity in Nigeria: Àwọn gómìnà ẹkùn Gúúsù fòfin de dída màálù ní gbangba

Oríṣun àwòrán, Dapo Abiodun MFR
Awọn gomina ilẹ Yoruba, ilẹ Ibo ati awọn ẹkun Niger Delta ti ke si Aarẹ Muhammadu Buhari lati b'awọn ọmọ Naijiria sọrọ lori eto abo to ti polukurumusu ni Naijiria bayii.
Awọn mẹtadinlogun lapa gusu orilẹede Naijiria kede ọrọ naa lẹyin ipade ti wọn ṣe lọjọ Iṣẹgun ninu Asaba, nipinlẹ Delta.
Koko mejila lawọn gomina naa fẹnu ko si eleyii ti alaga wọn, Gomina Rotimi Akeredolu ipinlẹ Ondo ka jade.
- Ikú kò m'ọmọdé, kò màgbà, ẹ gbàdúrà fún ìdílé mi àti aya pẹ̀lú ọmọ olóògbé- Pásítọ̀ Adeboye
- Mi ó ṣọ̀fọ̀, mo sọkún nítorípé... - Ìyàwó olóògbé Dare Adeboye sọ̀rọ̀ níbi ìsìn idágbére ọkọ rẹ̀
- Àwọn ọmọ Naijiria yóò rí akitiyan ìjọba láti yanjú ètò àbò tó mẹ́hẹ láìpẹ́ - Lai Mohammed
- Ìjọba àpapọ̀ kéde Òjọ́rú àti Ọjọ́bọ gẹ́gẹ́ bi ísinmi lẹ́nu iṣẹ́
- Ẹni tó bá ní láàkàyè, a mọ ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn, àwà ti kọ lẹ́tà, èsì t'Ọ́lọ́pàá sì fún wa rèé - Yomi Fabiyi
Awọn gomina naa sọ pe awọn eeyan apa gusu Naijiria ṣi n wa iṣọkan orilẹede yii niwọn igba ti ododo, aiṣegbe lẹyin ẹnikan ati alaafia ba ti wa laarin awọn ọmọ Naijiria.
Awọn ẹkun gusu ko ṣai fi aidunnu wọn han lori eto abo to mẹhẹ bayii.
''A ṣe akiyesi pe awọn darandarn, awọn ọdaran atawọn janduku to n wa si ẹkun gusu ni Naijiria ti ṣakoba fun eto abo awọn eeyan wa.
Eku ko ke bi eku mọ, bẹẹ ni ẹyẹ ko ke bi ẹyẹ mọ, awọn eeyan ko le gbe ni alaafia mọ.
Gbọgbo nkan yii lo si ti ṣokunfa ọwọngogo ounjẹ bayii.
Fun idi eyi, a ti fofin de dida maalu kiri ni gbangba kaakiri apa gusu Naijiria,'' Akeredolu lo sọ bẹẹ ninu atẹjade to fi sita.
Akeredolu ni ''a tun fẹnuko pe ijọba ni lati gbe igbesẹ ni kiakia lati lati ṣe atunto Naijiria lori ọrọ ọlọpaa ipinlẹ atawọn atunto ileeṣẹ ijọba kan.
A tun fẹ ijọba apapọ ṣe agbekalẹ ifọrọwerọ pẹlu awọn ọmọ Naijiria lati le sọ ohun to n kọ wọn lominu gan an.
Ijọba tun gbọdọ tun ero rẹ pa lori ofin konle-o-gbele to da pada tori ajakalẹ arun covid-19 nitori akoba to le ṣe fun ọrọ aje.
- Amotekun Ondo ju afurasí ajínigbé mẹ́rin s'átìmọ́lé, dóòlà àwọn tí wọ́n jígbé
- Emmanuel Abina, ọmọ Olùdarí ìjọ GOFAMINT, Elijah Abina jáde láyé lẹ́yìn ikú ìyàwó rẹ̀
- Báwo ni ìṣẹ̀lẹ̀ ikú Kayode Badru ṣe ṣẹlẹ̀ ní Celestial Church of Christ ni Eko? ẹ wo ohun tí a mọ̀!
- Àwọn agbébọn ya wọ mọ́ṣáláàṣí, wọ́n gbe èèyàn 40 lọ lásìkò àdúrà Tahajjud












