New Minimum Wage: Aráàlú fẹ́ kíjọba dín owó olóṣèlú kù dípò owó oṣù òṣìṣẹ́

Ẹgbẹ osisẹ n sewọde

Oríṣun àwòrán, NLC

Awọn ọmọ Naijiria fesi lori ẹrọ ayelujara lori igbesẹ ijọba lati din owo oṣu oṣiṣẹ ku lori ọrọ aje to dẹnukọlẹ

Igbe ilu o fararọ ni awọn eniyan nke ni Naijiria pẹlu ariwo pe ki ijọba wa nkan ṣe si ọwọngogo owo ounjẹ, ko ma si gbero lati din owo oṣu oṣiṣẹ, ti ko to nkankan ku.

Ọrọ yii ati bẹẹ bẹẹ lọ ni awọn eniyan n fi ranṣẹ ni oju opo ikansiraẹni Facebook lati fi aidunnu wọn han si ijọba to wa lode yii lori bi nkan ko ṣe fararọ fun awọn eniyan.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Ijọba orileede Naijiria lo kede wi pe awọn n gbero lati din owo oṣu oṣiṣe ku nitori ọrọ aje ti dẹnukọle patapata ni Naijiria.

Àkọlé fídíò, Oba Sunday Oyediran ṣàlàyé kíkún nípa ìṣẹ̀ṣe, ìgbàgbọ́ àti ẹ̀sìn tí kò dí ará wọn lọ́wọ́

Amọ, ẹgbẹ oṣiṣẹ ni Naijiria to fi mọ awọn araalu lo fi lede wi pe, ko gbọdọ si ohun to jọ bẹẹ, afi ti ijọba ba fẹ din owo oṣu awọn oloṣelu ku.

Adeniji Olugbenga to sọrọ loju opo BBC News Yoruba ni owo awọn aṣofin ni Naijiria ju ti awọn oṣiṣẹ lọ ni ọna igba.

O ni nitori idi eyi, ki ijọba din owo oṣu wọn ku, ki wọn fi ti awọn oṣiṣẹ silẹ nitori owo ọhun ko to ra nkankan pẹlu ọwọngogo owo ounjẹ.

Àkọlé fídíò, Francis Olusola Alao: Wọ́n ti ti ọ̀rọ̀ òṣèlú bọ ọ̀rs Sunday Igboho, ṣùgbọ́n..- Oba Olugbọn

Bolaji Abdullateef ni ijọba fẹ sọ awọn oṣiṣẹ to ti talaka tẹlẹ di ekute sọọṣi ti ko tilẹ lee fi owo ra nkankan mọ ni ọja, nitori gbogbo rẹ ti dojuru patapata.

Ninu ọrọ tirẹ, Oko Oro Wumi beere pe se ni asiko ti gbogbo nkan wọn gogo yii ni ijọba n gbero lati din owo oṣu ku, nigba to si jẹ pe owo ori awọn oṣiṣẹ yii ni awọn adari Naijiria n na lai ṣiṣẹ fun un.

Adenike Ireoluwa Amoo ni owo oṣu ti awọn oṣiṣẹ n gba lọwọlọwọ ni Naijiria ko ka nkankan ati pe aanu Ọlọrun ni wọn fi n gbera, ti ọpọlọpọ oṣiṣẹ si ti di onigbese tan.

Àkọlé fídíò, hhhhhh

Pẹlu ibinu ni Olakunle Timothy Orokunbi fi sọ wi pe ki ijọba lọ din owo oṣu ti gomina kọọkan n gba ku pẹlu owo mọto wọn.

Bakan naa lo ni owo aṣọ ti wọn n wọ, owo ijoko ile awọn aṣofin ati owo oṣu awọn minisita ni ki ijọba lọ dinku, kii ṣe ti awọn oṣiṣẹ.

Amọ, arakunrin Olatunde Awe O'Connell ni ki ijọba Naijiria ṣe ohun gbogbo ti wọn ba le ṣe lati ri wi pe ọrọ aje to dẹnukọlẹ bọ si ipo pada ni Naijiria.