Oba Abdul-Rauf Olayiwola Adedeji II : Wo ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa Akirun ti Ìlú Ìkìrun tó wàjà

Oríṣun àwòrán, Tkbeshi Online
Ijọba ipinlẹ Osun lo kede loju opo Twitter rẹ pe Akirun ilu Ikirun, Oba AbdulRauf Olawale Adedeji waja lalẹ Ọjọru
Ijọba Osun ṣalaye loju opo Twitter rẹ pe ni bii ago mọkanla alẹ Ọjọru ti Oba Adedeji dagbere faye.
Ko si ẹni to le sọ pato ohun to ṣekupa Akirun ilu Ikirun lẹni ọdun mejidinlọgọrin.
- Mo kọ̀ láti pokùnso nítorí pé mo ní 'Cancer'- Iwalade
- Inú mi kò bá dùn tí wọ́n bá le fi àwọn ọlọ́pàá tó lù mí jófin yàtọ̀ sí N5m tí wọ́n fẹ́ fún mi- Tola
- A kò kórira àwọn Fulani, àwọn ọ̀bàyéjẹ́ ìnú wọ́n ni á kò fẹ́ - Ọba Akintunde ni ẹkùn Yewa, ìpínlẹ̀ Ogun
- Ọkùnrín márùn ún fojúbalé ẹjọ́ lórí ẹ̀sùn ijà àti igbó fífà ní gbangba
- Awakọ̀ ojú pópó láti Eko san N26,000 nítorí ó lu òfin tó de ìtànkálẹ̀ ààrùn Covid-19 - FRSC
Ohun ti a gbọ ni pe Akirun ṣe aisan diẹ ki Ẹlẹmi to gba a lalẹ Ọjọru.
Bi ọgbọn ọdun sẹyin ni Oba Adedeji gori itẹ baba rẹ nilu Ikirun.
Ọpọ eeyan lo ṣapejuwe Oba Adedeji to jẹ oṣiṣẹ banki tẹlẹ ki o to jọba pe musulumi ododo ni.
Ogunna gbongbo ẹgbẹ musulumi nii ṣe nilu Ikirun ati ni ipinlẹ Osun lapapọ nigba aye rẹ.
Ọdun 2002 ni Oba Adedeji lọ si ilẹ mimọ ni ilu Mecca.

Oríṣun àwòrán, Google
Oun ni baba iṣalẹ ẹgbẹ musulumi Ibadu-Rahman Society ati Anwar-Ul-Islam niluu Ibadan nigba aye rẹ.
Oba Adedeji lo ọrọ rẹ Eledua yọnda fun un lati ṣe iranwọn fawọn ti ko rọwọ họri lawujọ.
Ìròyìn Yàjóyàjó -'Akirun ti Ìlú Ìkìrun,Oba Abdul-Rauf Olayiwola Adedeji II ti wàjà
Ọba Akirun ti Ikirun, Oba Abdul-Rauf Olayiwola Adedeji II ti jade laye.
Eni ọdun mejidinlọgọrin ni ọba ni ipinlẹ Osun naa ki wọn to jade laye.


















