Yoruba Nollywood: Àgbà òṣèré tíátà, Musiliat Arikeusola 'Osuntoun' jáde láyé

Iya Osuntoun

Oríṣun àwòrán, OTHER

Iku tun ti mu ọkan gboogi laarin awọn agba oṣere tiata Yoruba lorilẹede Naijiria, Alhaja Musiliat Arikeuọọla ti ọpọ mọ si Ọṣuntoun lọ.

Gẹgẹ bi iroyin ti a gbọ, opin ọsẹ yii naa ni Alaaja Ọṣuntoun jade laye lẹni ọdun mẹtadinlaadọrin.

Ko si ẹni to ba n wo awọn ere ibilẹ Yoruba to kun fun aṣa, iṣe ati igbagbọ ẹya Yoruba ti ko ni mọ mama, Ọṣuntoun paapaa julọ nitori awọn ipa awọn "ẹlẹmi agba" to ko ninu awọn ere oloogbe Yẹkini Ajilẹyẹ.

Ile rẹ lagbegbe Ijẹtu nilu Osogbo ni Mama dakẹ si.

Akọwe fun ẹgbẹ awọn onitiata ni ipinlẹ Ọṣun, Ademọla Adedokun fi idi iroyin iku rẹ mulẹ fun awọn oniroyin.

Lara awọn ere ti oloogbe Osuntoun ti kopa ni Koto Orun, Aye Akamara, Koto Aye, ti gbogbo rẹ jẹ latọwọ oloogbe Ajilẹyẹ.

Oloogbe Ọṣuntoun funrarẹ naa gbe awọn ere kan jade bii 'Omi Ipin,' 'Imi Esin' ati 'Ogun Omo Iya le', to jẹ ere ti o ṣe gbẹyin, gẹgẹ bi ọgbẹni Adedokun ṣe sọ.

Àkọlé fídíò, Tóò bá fún ọkùnrinn lóúnjẹ́ tóo tẹ́ kiní yẹn sílẹ̀ fún un dáadáa... - Yinka TNT