Coronavirus: Ilé aṣojú-ṣòfin tako kíkó ọmọ Nàìjíríà wálé láti China

Ile aṣoju-ṣofin l'Abuja

Oríṣun àwòrán, Twitter/House of Reps NGR

Ile aṣoju-ṣofin gbona janjan lọjọ Iṣẹgun nigba ti wọn jiroro lori aba lati ko awọn ọmọ Naijiria to wa lorilẹede China wale, nitori aarun coronavirus to n ran kaakiri lorilẹede naa, bi ina inu ọyẹ.

Ṣugbọn lẹyin ọ rẹyin, ile pada fẹnu ko, lati tako aba kiko awọn ọmọ Naijiria to wa ni China wale.

Ohun ti ile sọ ni pe, orilẹede China ni awọn irinṣẹ igbalode nile iwosan ti wọn le fi dena aarun coronavirus ju Naijiria lọ.

Bi adari ile, Femi Gbajabiamila se gbiyanju to lati parọwa fawọn aṣofin pe ki wọn tiẹ gbọ tẹnu aṣofin to mu aba naa wa, Benjamin Okezie, n ṣe ni wọn faake kọri, ti wọn ko si fun un lanfaani lati sọrọ.

Ohun to ya ọpọ lẹnu ni pe, awọn aṣofin meji mii to wa lara awọn to ṣagbatẹru aba naa kọ lati ṣe atilẹyin fun aṣofin Okezie nigba ti ọrọ naa di ede aiyede nile.

Ile aṣoju-ṣofin l'Abuja

Oríṣun àwòrán, Twitter/House of Reps NGR

Ẹwẹ, aṣoju orilẹede China ni Naijiria, Zhou Pingjian sọ pe, ọgọta ọmọ Naijiria lakọsilẹ fihan pe o wa niluu Wuhan ti aarun coronavirus ti bẹrẹ gan.

Ṣugbọn Ọgbẹni Pingjian sọ pe, ko si ọmọ Naijiria kankan to tii lugbadi aarun coronavirus.