Balogun Fire: Ilé ìtajà alájà mẹ́rin ni iná náà ti kọ́kọ́ sẹyọ

Ọ̀ga àgbà àjọ LASEMA Femi Osanyitolu, sàlàye pe ni kété ti àwọn de ibi ìṣẹ̀lẹ̀ náà ni àwọn ti ri pé ilé alájà mẹrin kan ni ìnà náà ti bẹ̀rẹ̀.
O sálàyé pé ǹkan to fa ìṣẹ̀lẹ̀ náà ni bi àwọn ènìyàn ṣe n ko epo pamọ lanà ti kò dára lo ṣẹ iná yẹ
- Ọmọ Yahoo yóò pọ̀ si tẹ bá ní kí ọ̀kadà má rìn lójú pópó Eko - Àwọn ọ̀dọ́
- "Ọlọ́pàá ní kí n bọra sílẹ láti mọ bóyá obìnrin ní mí torí mo ní irùngbọ̀n"
- Ààbò Naijiria tó dojúrú, ẹ gbé ọ̀rọ̀ ọlọ́pàá abẹ́lé wò bóyá yóò san wá - Ilé aṣojú-ṣòfin
- Ọ̀gọ́rún sọ́ọ̀bù, àìmọye dúkìá ni iná tún jó lọ́jà Sabo nílùú Sagamu
Fidio bi ina se jo ọja Balogun ree:
O ni láti ibẹ̀ lo ti fò mọ ilé méje míràn sùgbọ́n àjọ LASEMA ní àwọn ti ń kápa rẹ ti àwọn si ti wó ilé méjé ti iṣẹ̀lẹ̀ náà de bá
Gbogbàwọn àjọ to yẹ lo ti wà nilẹ̀, ti Osanyitolu si ti rọ gbogbo àwọn ènìyàn láti lo fi ọkàn wọ́n

Ó ṣeéṣe kó jẹ́ ọyẹ́ tó ń mú lásìkò yìí ló fa ìjàmbá iná lọ́jà Balogun - LASEMA

Isẹlẹ ina to n jo lemọlemọ lẹnu lọọlọ yii tun ti na ọwọja rẹ de gbajugbaja ọja Balogun nilu Eko, to si nawọ gan ibudo itaja mẹrin ọtọọtọ.
Nigba to n ba BBC Yoruba sọrọ akọtun isẹlẹ naa, oludari ajọ to n risi isẹlẹ pajawiri nipnlẹ Eko, LASEMA, Femi Oke Ọsanyintolu, salaye pe oun ko tii le sọ ohun to se okunfa ijamba ina ọhun.
Ọsanyintolu ni o seese ko jẹ asiko ọyẹ taa wa yii lo mu ki isẹlẹ ina ọhun waye, gẹgẹ bo se n sẹlẹ kaakiri agbegbe wa lẹnu lọọlọ yii.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ọmọ Yahoo yóò pọ̀ si tẹ bá ní kí ọ̀kadà má rìn lójú pópó Eko - Àwọn ọ̀dọ́
- Ààbò Naijiria tó dojúrú, ẹ gbé ọ̀rọ̀ ọlọ́pàá abẹ́lé wò bóyá yóò san wá - Ilé aṣojú-ṣòfin
- "Ọlọ́pàá ní kí n bọra sílẹ láti mọ bóyá obìnrin ní mí torí mo ní Irungbọ̀n"
- Ọ̀gọ́rún sọ́ọ̀bù, àìmọye dúkìá ni iná tún jó lọ́jà Sabo nílùú Sagamu
- Malami, IGP àti alága APC Oyo ni yóò káwọ pọ̀'yìn rojọ nítori àwọn alaga Kansu tẹlẹri
- Ẹ ta kété sí àjọṣepọ̀ tí kò bá fún yín láyọ̀ torí ẹ̀mí kò ní ààrọ̀ - Àwọn òṣèré tíátà gbarata lórí ìdájọ́ ikú
- Ojora ń mú mi lọ́wọ́ lórí ìkọlù tó wáyé, ara mi kò tíì balẹ̀ - Toyosi Adesanya
LASEMA ni opopona Martins ti ina ti sọ nijooni, naa tun ni ijamba ina mii ti n waye lọwọlọwọ bayii, ti awọn osisẹ ajọ naa ati awọn panapana si ti de sibi isẹlẹ ọhun lati tete bomi pa ina naa ki ọwọja rẹ to kọja aala.

Oríṣun àwòrán, LASEMA
O fikun pe ko sẹni to lee se odiwọn ọsẹ ti ina naa ti se nitori pe o si n jo lọwọ, amọ ni kete ti ọwọja rẹ ba ti lọ silẹ, ni awọn yoo fi ikede sita lati salaye lẹkunrẹrẹ nipa isẹlẹ naa.
Bẹẹ ba gbagbe, igba meji ọtọọtọ ni awọn ile itaja jona ni ọja Balogun lọdun to kọja, ti ọkẹ aimọye dukia si baana.
Ọ́pọ awọn ontaja si la ri ti wọn n wọ inu ina lati ko ọja wọn jade ko maa baa jona, eyi to lewu pupọ.
Ìròyìn Yàjóyàjó - Iná sọ nílé ìtajà mẹ́rin lọ́jà Balogun l'Eko
Ìròyìn tó ń tẹ̀ wa lọ́wọ́lọ́wọ́ ní wí pé ile itaja mẹrin ni ọja Balogun lo n jona lọwọ lọwọ bayii.

Oríṣun àwòrán, LASEMA
Bi o tilẹ jẹ pe ko si ẹni to tii lee salaye ohun to fa ina ọhun, sibẹ a ko tii kofiri awọn osisẹ panapana nibẹ́.
Ko si si ẹni to lee sọ iye dukia to jona nitori ina ọhun si n jo lọwọ.
A n se akojọpọ ẹkunrẹrẹ iroyin yajoyajo lọwọ, a o maa gbe ẹkunrẹrẹ iroyin naa sori atẹ iroyin wa laipẹ. Ẹ jọwọ, ẹ tun oju opo iroyin yi yẹwo, ki ẹ lee ri ẹkunrẹrẹ iroyin ọtun laipẹ.

















