Border Closure: Iléeṣẹ́ asọ́bodè tí kéde ọjọ tí wọn yóò ṣí ẹnu ibodè Nàìjíríà padà

Oríṣun àwòrán, Facebook/customsng
Fawọn to ba lero pe ileeṣẹ aṣọbode Naijria yoo jẹ ki awọn ọja kan wọle lasiko Keresimesi ti n bọ yii ,ọrọ ko ri bẹẹ.
Idi ni pe Ileeṣẹ aṣọbode orileede Naijiria ti sun ọjọ ti wọn yoo ti ibode Naijiria pẹlu awọn alabagbe rẹ pa titi di oṣu kini ọdun 2020.
Ikede yii ti wọn fi ista ninu atẹjade kan ni ọga ileeṣẹ naa kan Victor Dimka buwọlu lọjọ kini oṣu Kọkanla ọdun 2019.
Ninu iwe naa, ileeṣẹ naa sọ pe t'oun ti bi awọn ti ṣe ṣe aṣeyọri to lamilaka pẹlu bode tawọn ti pa 'ASarẹ Buhari ṣi ni ki awọn tẹiwaju pẹlu titi ibode naa di oṣu Kini ọdun 2020.''
O tẹsiwaju pe owo ajẹmọnu awọn oṣiṣẹ ileeṣẹ aṣọbode to fi mọ owo epo ọkọ ti wọn yoo lo yoo jẹ ssisan laipẹ.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Sumner Shagari Sambo
Bi a ko ba gbagbe orileede Naijiria gbe igbesẹ lati ti ibode rẹ pẹlu awọn orileede to jẹ alabagbe rẹ lati le dẹkun fayawọ irẹsi ati awọn nkan tẹnu n jẹ miiran.
Igbesẹ yi tawọn kan sọ pe o tako ofin karakata ajọ ECOWAS ni o ti mu ki awọn alabagbe Naijiria bi Benin ati Ghana ma kerora.
Koda awọn orileede miiran bi Thailand ati Vietnam naa ke gbajare si ijọba Naijiria lati ṣi ibode ki awọn ọja wọn baa le wọle.












