Xenophobia: Àbọ̀ ààrẹ Muhammadu Buhari rèé láti ilẹ̀ South Africa

Oríṣun àwòrán, Twitter/Bashir Ahmad
Aarẹ Muhammadu Buhari ti pada si olu ilu orilẹede Naijiria, Abuja lọjọ Ẹti lẹyin abẹwo ọlọjọ meji si orilẹede South Africa.
Aarẹ Buhari ṣe oniruuru ipade pẹlu aarẹ ilẹ South Africa, Cyril Ramaphosa lori ibaṣepọ laarin awọn orilẹede mejeeji.
Ikọlu awọn ọmọ Naijiria laipẹ yii jẹ ọka gbogii ninu ọrọ tawọn olori orilẹede mejeeji jọ sọ.
- Lẹ́yìn ọ̀ rẹyìn, ilé ẹjọ́ gba oníduro Sowore pẹ̀lú ọgọ́rùn ún mílíọ̀nù náírà
- Ìjọba máa ní láti dá òsìsẹ́ dúró kí wọ́n tó lè san gbedéke owó osù tí ẹ fẹ́ - Ngige
- Mo sọkún bíi ọmọ́dé nígbà tí à ń gbé òkú àwọn èèyàn jáde - Imam tó gba àwọn Krìstẹ́nì là
- Bàbá ọlọ́mọ méjì kú sínú àgbàrà òjò
- Ẹ yéé purọ́ kiri! Ìdí rèé tí Aisha Buhari kò tíì padà sí Nàìjíríà- Iléeṣẹ́ ààrẹ
- Ẹ ṣé mo dúpẹ́ fún àdúrótì àti ìfẹ tí ẹ ní sí mi - Toyin Abraham
Aarẹ Buhari fi aidunnu rẹ si bi awọn ọmọ South Africa ti fiya jẹ awọn ọmọ Naijiria ti wọn n ṣe atipo lorilẹede South Africa.
Aarẹ Ramaphosa tọrọ aforiji lọwọ Aarẹ Buhari lori bi awọn ọmọ South Africa ti ba ọpọ dukia awọn ọmọ Naijiria jẹ ninu ikọlu ọhun.

Oríṣun àwòrán, Twitter/Bashir Ahmad

Oríṣun àwòrán, Twitter/Bashir Ahmad
Ẹwẹ, ile iṣẹ ọkọ ofurufu Air Peace ti ko awọn Naijiria bi igba meji pada sile lẹyin iṣẹlẹ ikorira alejo to waye ni South Africa.








