South Africa killings: Sanwo-Olu ní àwọn ọmọ Nàìjíríà tó gbẹ̀san ìkọlù àjòjì ní South Africa ti yọ ọmọ Nàìjíríà 5000 níṣẹ́ l'Eko

Gomina Sanwo-Olu n ṣabẹwo sawọn ile itaja ti wọn kọlu

Oríṣun àwòrán, @jidesanwoolu

Ṣe awọn agba bọ wọn ni ọrẹ mi yaso emi naa a ya temi, afaimọ konitọun ma ṣe gaa sara

Eyi gan an lo difa fawọn to kọlu awọn ileeṣẹ to lọwọ orilẹede South africa ninu nilu Eko nitori ikọlu awọn ajoji to n waye lorilẹede South Africa.

Ni bi a ti ṣe n sọrọ yii, ẹgbẹrun marun eeyan lo ti padanu iṣẹ wọn nipinlẹ Eko nitori ikọlu ẹlẹsan tawọn ọmọ Naijiria kan ṣe sawọn ileeṣẹ ti wọn wo pe awọn ọmọ orilẹede South africa ni nilu Eko.

Gomina Sanwo-Olu n ṣabẹwo sawọn ile itaja ti wọn kọlu

Oríṣun àwòrán, @jidesanwoolu

Gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-olu lo fẹ idi ọrs yii sita lasiko abẹwo rẹ sawọn ileeṣẹ ati ohun elo tawọn olufẹhonuhan bajẹ nilu Eko lasiko ti wọn fi nkọlu awọn ohun to jẹ tawọn ọmọ ilẹ South Africa naa.

Gomina Sanwo-Olu koro oju si bi awọn eeyan kan ṣe lo anfani iṣẹlẹ naa lati lọ maa fọ awọn ile itaja nlanla l'Eko.

O ni ọrọ naa ti di ti papa to n pa ara rẹ to ni oun n pa aja; nitoripe pẹlu ikọlu ọhun awọn ọmọ orilẹede Naijiria gan lo fara ko iṣẹlẹ naa.

Àkọlé fídíò, Mutallab‘s Father: Ọmọ mi ti kábàmọ́ọ̀ ìwà tó wù, ẹ ṣàánú rẹ̀