Afe Babalola: Adarí Nàíjíríà kankan kò leè ṣàṣeyọrí pẹ̀lú òfin ọdún 1999

Oloye Afe Babalola

Oríṣun àwòrán, @hartarmah1

Agba amofin nni, Afẹ Babalọla ti kede pe ofin ti orilẹede Naijiria n lo lọwọlọwọ bayii ko kun to, to si mẹhẹ lati yanju oniruuru isoro to n ba orilẹede yii finra.

Ilu Ado Ekiti ni Afẹ Babalọla ti woye ọrọ yii lasiko ti ajọ isọkan ilẹ Afirika n fi oye Awokọse rere nilẹ Afirika da lọla.

Babalọla ni ofin ilẹ wa tọdun 1999 jẹ adina fun eto idagbasoke ati ilọsiwaju Naijiria taa ba wo ọpọ kudiẹ-kudiẹ to wa ninu amulo ati amusẹ rẹ.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

O ni yoo nira pupọ, ti yoo si jẹ isoro nla fun eyikeyi adari orilẹede Naijiria lati se aseye ti alakan n se epo lori aleefa, ta ba si n lo ofin naa, pẹlu afikun pe ofin ọdun 199 kogbewọn to fun irufẹ akanda orilẹede ti Naijiria jẹ.

Babalọla ni ayafi ti a ba gbe igbesẹ akin lati mu ayipada ba ofin ọdun 1999 naa, se ni ọps aayan wa lati se aseyọri yoo maa ja si asan.

Oloye Afe Babalola

Oríṣun àwòrán, @hartarmah1

Bakan naa ni agba amofin yii tun woye pe, ba se n pe ofin ilẹ wa naa ni 'ofin apapọ Naijiria' jẹ eyi ti ko bojumu to, nitori ofin to wa fun igun kan ni.

Afẹ Babalọla wa rọ aarẹ Muhammadu Buhari lati pe ipade apero apapọ awọn ọmọ Naijiria, ta si mu awọn asoju lai lo ẹgbẹ oselu kankan.

O ni nibi ipade yii ni wọn yoo ti gbe ofin kalẹ fun Naijiria eyi ti yoo foju sun idagbasoke awọn ọmọ orilẹede yii.