Bola Ahmed Tinubu: Wo ǹkan tó yé kí o mọ̀ nípa Bola Ahmed Tinubu, ààrẹ tuntun ní Nàíjíríà

Asiwaju Bola Ahmed Tinubu

Oríṣun àwòrán, @BATofficial

Bola Ahmed Tinubu, to jẹ ẹni aadọrin ọdun ni ọpọ gbagbọ pe oun lo tun ilu Eko ṣe, ti ipinlẹ naa fi di eyii to ni ọrọ aje nla.

Gẹgẹ bii oludije sipo Aarẹ labẹ asia ẹgbẹ oṣelu APC, Tinubu n koju atako lati inu awọn ẹgbẹ oṣelu mii bii PDP ati LP.

Gẹgẹ bii ẹni to ti sa kuro ni Naijiria ri lọ silẹ okeere lasiko iṣejọba Abacha, ami idanimọ rẹ, eyii to maa n wa ni gbogbo fila rẹ ni ti ṣẹkẹṣẹkeẹ to ti ja, eyii to farajọ nọmba '8.'

Tinubu kẹkọọ gboye ninu eto iṣiro, o si ti fi akoko igba kan jẹ oṣiṣẹ ileeṣẹ to n wa epo rọbi, iyẹn Mobil.

Ni bayii to n dije du ipo Aarẹ, Tinubu ti ri ipo naa gẹgẹ bii ẹtọ rẹ ati ere lẹyin iṣẹ to ti ṣe lati gbe awọn eeyan kan dide ninu oṣelu Naijiria.

bbc

Eredi ree to fi sọ niluu Abeoku lọdun to kọja pe " Emi lokan."

Lootọ ni Tinubu ni ọpọ iriri ninu eto oṣelu, eyii si jẹ ọkan lara awọn koko ti awọn ololufẹ rẹ fi n polongo ibo fun un.

Ti gomina ipinlẹ Eko nigba kan ri naa ba jawe olubori, lara awọn nnkan ti yoo dojukọ gẹgẹ bii Aarẹ ni iṣoro eto abo, airiṣẹ ṣe laarin awọn ọdọ ati iṣọkan Naijiria to n mi lẹsẹ.

Amọ awọn ipenija wọnyii ko mi Tinubu laya, gẹgẹ bo ṣe maa n sọ pe oun ni iriri to dantọ gẹgẹ bii gomina ipinlẹ Eko laarin ọdun 1999 si 2007.

Lasiko iṣejọba rẹ bii gomina Eko, o ṣe afikun lọpọlọpo si iye owo ti ipinlẹ naa n pa wọle laarin oṣu kan, o si gbiyanju lati din sunkẹrẹ fakẹrẹ ọkọ oju popo ku.

Lagos

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Awọn Esun ti wọn ti fi kan Tinubu?

Ṣugbọn lẹyin to ti kuro lori aleefa, ọpọ eeyan lo n sọ pe ilu Eko kii ṣe 'maga city' bi awọn alatilẹyin rẹ ṣe n sọ nitori awọn nnkan ti ko si nibẹ, to fi mọ awọn inira ti ọpọ olugbe ipinlẹ naa n lakọja lojojumọ.

Yatọ si eyii, ọpọ eeyan lo fẹsun kan Tinubu pe oṣooṣu lo n gba obitibiti owo lọwọ ijọba ipinlẹ ọhun, amọ o ti sọ pe irọ nla ni ẹsun yii.

Gbobgo awọn to ti jẹ gomina lẹyin Tinubu lo jẹ awọn ọmọlẹyin rẹ ninu oṣelu, a tilẹ gbọ pe ẹni to ba kọ lati ṣe ti Tinubu ko ni tọ ipo gomina Eko wo lailai.

Awọn kan tun fẹsun ajẹbanu kan agba oloṣelu ọhun amọ gbogbo ẹṣun naa lo ni kii ṣe ti oun.

Lọdun meji sẹyin, Dapo Apara to jẹ oluṣiro owo nileeṣẹ Alpha-beta fẹsun kan Tinubu pe o n lo ileeṣẹ naa, ti ọpọ gbagbọ pe o lọwọ ninu idasilẹ rẹ, lati ko owo ilu lọ silẹ okeere.

Tinubu ṣe ẹsun yii, koda o gbe ọgbẹni naa lọ silẹ ẹjọ, amọ lẹyinorẹyin, wọn pari ọrọ naa ni itubi inubi.

Ninu eto idibo to kọja, ọkọ ti awọn banki fi n ko owo 'bullion van' wọ inu ile Tinubu, eyii ti awọn eeyan sọ pe wọn fi ṣe magomago ninu idibo naa, amọ Tinubu ko sẹ ọrọ naa, o si sọ pe oun ko ji owo ijọba ko, beẹ si ni ki ẹnikẹni to ba ni ẹsun lati fi kan oun gbọdọ mu ẹri to dantọ jade.

Bola Tinubu

Oríṣun àwòrán, @OFFICIALABAT

Tinubu lori ọrọ Lekki Toll Gate:

Ọpọ awọn ọdọ lo tun maa n naka abuku si Tinubu latari iṣẹlẹ iṣekupani to waye ni iloro Lekki Toll Gate ni ogunjọ, oṣu Kẹwaa, ọdun 2020.

Ni bayii ti eto idibo gbogbogbo ti sunmọle, ọpọ eeyan lo n sọ pe Tinubu ko gbadun, o si ni lati ṣetọju ara rẹ dipo ko maa du ipo Aarẹ.

Lara awọn to ni irufẹ ero bayii yatọ si ọpọ araalu ni Reno Omokri, Dino Melaye, atawọn eeyan pataki mii ni Naijiria.

Wọn ni ko yẹ ki Naijiria tun ṣe aṣiṣe lati yan Aarẹ ti yoo maa fi gbogbo igba lọ soke okun fun itọju ilera rẹ.

Wayi o, boya Tinubu jawe olubori ninu idibo ọdun yii tabi beẹ kọ, Aarẹ tuntun ti yoo gba ijọba lọwọ Buhari yoo ni ọpọ iṣoro lati tan.

Ọpọ ọmọ Naijiria lo si gbagbọ pe Naijiria yoo ṣi dara bo tilẹ jẹ pe pupọ ninu wọn lo ti n japa.

bbc

Àwọn ta ló ń díje láti tukọ̀ Naìjíríà?

Mọ̀ síi nípa àwọn tó ń du ipò ààrẹ Nàìjíríà

Ya olùdíje kan nítorí kí o lè kà nípa wọn

Bola Tinubu

All Progressives Congress (APC)

  • Ọjọ́ orí: 70
  • Ó gba oyè nípa ìmọ̀ ìṣirò ní fásitì ìpínlẹ̀ Chicago (Chicago State University)
  • Ó ṣe gómìnà ìpínlẹ̀ Eko fún sáà méjì láti 1999 sí 2007
  • Ó ṣojú [wọ̀ Oòrùn ìpínlẹ̀ Eko ní ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà láti 1992 sí 1993.
  • Ó jẹ́ èèyàn kan tó ti pẹ́ nhí ìdí òṣèlú Nàìjíríà, ìgbà àkọ́kọ́ tí yóò du ipò ààré nìyí.
  • ìgbógun ti ìṣèjọba sójà
  • Mú ìdàgbàsókè bá owó tó wọlé fún ìpínlẹ̀ Eko ní ọ̀nà tó ju ìlọ́po mẹ́rin lọ láti N22.2 blilion ní 1999 sí N220.9 bíllion ní 2007.
  • Ó ṣiṣẹ́ bíi ọ̀gá tó ń ṣe àyẹ̀wò ìwé owó, lẹ́yìn náà ló ṣe iṣẹ́ akápò ní iléeṣẹ́ Mobile Producing Nigeria, ọ̀kan lára iléeṣẹ́ epo tó tóbi jù ní Nàìjíríà.
  • Láti ṣé àlékún ọjà tí Nàìjíríà ń tà síta àti láti dín ìgbẹ́kẹ̀lé Nàìjíríà kù lóríiohun òkèrè.
  • Láti sọ àìníṣẹ́ ṣe láàrin àwọn ọ̀dọ́ di ìlàjì láàrin ọdún mẹ́rin àti láti pèsè iṣẹ́ mílíọ́nù kan nípa ìmọ̀ ẹ̀rọ kọ̀pútà láàrin ọdún méjì.
  • Mú àyípadà bá ètò ìdájọ́ kó lè mójútó ìdènà ìrúfin àti ṣe àlékún ìfọkàntán lórío àwọn agbófinró.

Atiku Abubakar

Peoples Democratic Party (PDP)

  • Ọjọ́ orí: 76
  • Igbákejì ààrẹ Naìjíríà láti ọdún 1999 sí 2007.
  • Ó kàwé gboyè eléèkejì (masters) lórí àjọṣepò àwọn orílẹ̀èdè (International Relations) láti fásitì Anglia Ruskin University , UK.
  • Ó jẹ́ ẹni tó ṣe iṣẹ́ aṣọ́bodé rí kó tó di olóṣèlú láti nǹkan bíi ọdún 1980.
  • Ó du ipò ààrẹ náà ní ẹmaàrú ùn ní ọdún 1993, 2007,2011, 2015 àti 2019, ṣùgbọ́n kò wọlé.
  • Òun ló dá fásitì Amẹ́ríkà ti Nàìjíríà (American University of Nigeria) silẹ̀, fasitì náà fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́bìnrin Chibok ní ẹ̀kọ́ ọ̀fẹ́.
  • Oníṣòwò tó ṣe àṣeyọrí tó ní okòwò níbi ọ̀rọ̀ epo, ọ̀gbìn, bánkì àti ògùn.
  • Ètò títa iléeṣẹ́ ìjọba tó ní àríyànjiyàn nínú.
  • Fún àwọn aládáni ní ipa tó pọ̀ nínú ètòi ọrọ̀ ajé.
  • Fún ìṣọ̀kan orílẹ̀èdè ní agbára síi nípa ìṣe déédéé àti ìdájọ́ òdodo láàrin àwọn ẹ̀yà tó ń gbé ní Nàìjíríà.
  • Ṣe àtúntò ètò ìṣèjọba Nàìjíríà.

Peter Obi

Labour Party

  • Ọjọ́ orí: 60
  • Gómìnà tó ṣe sáà méjì ní ìpínlẹ̀ Anambara láti ọdún 2007 sí ọdún 2014.
  • Ó du ipò igbákejì ààrẹ ní ọdún 2019.
  • Oníṣòwò tó kàwé gboyè nípa ìmọ̀ ẹ̀kọ́ ọgbọ́n (Philosophy) ni University of Nigeria Nsukka.
  • "o bá ìpínẹ̀ rẹ̀ dá okòwo ''sub soveriegn wealth fund '' tó tó $156 million ní ìgbà tó fẹ́ fi orí oyè sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bíi gómìnà.
  • Ó gbé ìpínlẹ̀ Anambara lọ sí ipò kínní láti ipò kẹrìndínlọ́gbọ̀n nínú àwọn ìpínlẹ̀ Nàìjíríà lórí ìdánwò NECO àti WAEC.
  • Ó ní àwọn ṣọ́ọ̀bù alágbàtà kan tó fún ẹgbẹgbẹ̀rún èèyàn ní iṣẹ́.
  • Ó ṣèlérí láti kó àkóyawọ́ la'ti ríi pé ìjọba gbógun ti ìwà àjẹbánu.
  • Ó ṣèlérí láti gbé Nàìjíríà dé ibi ṣíṣe nǹkan láti ibi lílo nǹkan.
  • Ó ṣèlérí láti gbé ọlá fún ìdàgbàsókè àwọn èèyàn nípasẹ̀ fífi owó sí ẹ̀kọ́ ìmọ̀ ẹ̀rọ àti sáyẹ́sì, ètò ìlera àti àwọn nǹkan amáyédẹrùn.

Rabiu Kwankwaso

New Nigeria Peoploes Party (NNPP)

  • Ọjọ́ orí:66
  • Mínísítà fún ètò ààbò láti ọdún 2003 sí ọdún 2007
  • Gómìnà ìpínlẹ̀ Kano láti ọdún 1999 sí ọdún 2003, àti láti ọdún 2011 sí ọdún 2015.
  • Ó ṣojú agbègbè Madobi ní ilé ìgbìmọ̀ aṣojúṣòfin n;i ọdún 1992 àti ààrin Kano ní ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà láàrin ọdún 2015 sí ọdún 2019.
  • Ó kàwé gboyè PhD ní orí ìmọ̀ ẹ̀rọ ilé kíkọ́ láti fásitì Sharda ní India.
  • Ètò ẹ̀kọ́ ọ̀fẹ́ àti ìtọrẹ.
  • Ó ṣe àfikúnb iye àwọn tó wọ ilé ẹ̀kọ́ alákọ́bẹ̀rẹ̀ láti mílíọ́nù kan lọ́dún 2011 sí mílíọ́nù mẹ́ta ní ọdún 2015 nígbà tó kúrò lórí oyè.
  • Ó pèsè oúnjẹ ọ̀fẹ́ àti aṣọ ilé ẹ̀kọ́ ọ̀fẹ́ fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ní ilé ẹ̀kọ́ alákọ́bẹ̀rẹ̀.
  • Ó dá fásitì Sáyẹ́nsì àti ìmọ̀ ẹ̀rọ ìpínlẹ̀ Kano sílẹ̀ ní Wudil sílẹ̀. Ó tún dá Northwestern University sílẹ̀. Àwọn fásitì ìpínlẹ̀ Kano méjéjì.
  • Ó ṣe ìlérí láti pèsè iṣẹ́ nípasẹ̀ ìdókòwò lórí ètò ọ̀gbìn.
  • Kojú ètò ààbò tó mẹ́hẹ.
  • Ó ṣe ìlérí láti tẹ̀lé òfin àti ìlànà tó tọ́.