Social media abuse: Oyedepo ní àlòjù Twitter, Facebook àti Instagram máa ń ṣàkóbá fún àyànmọ́ ẹ̀dá

Oríṣun àwòrán, Oyedepo
Oludari agba fasiti Covenant to wa niluu Ota, nipinlẹ Ogun, Ọmọwe David Oyedepo ti gbawọn ọdọ ni imọran lati ye wa lori ẹrọ ayelujara ni gbogbo igba.
Biṣọọbu ijọ Living Faith ti ọpọ mọ si Winners Chapel sọrọ yii nibi ayẹyẹ ikẹkọọ jade fasiti Covenant ẹlẹẹkẹẹdogun rẹ lọjọ Ẹti.
- Kí ni IMEI ara fóònù àtí ìwúlò rẹ̀, tí ìjọba fi ń béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ aráàlú?
- Ajimobi kò ṣe NYSC tó fi di gómìnà, àmọ́ wọ́n yọ mí ní Mínísítà torí ẹ̀ṣùn yìí - Adebayo Shittu
- Ẹ wo ọ̀nà mẹ́jọ tí ìkọlù Israel fi ṣe àkóbá ńlá lórí ìgbé ayé aráàlú Gaza
- N kò tako Yoruba Nation, ohun tí mo sọ nípa Sunday Igboho rèé - Aseyin
- Alimotu Pelewura, Ìyálọ́jà akọ́kọ́ l’Eko tó mi amúnisìn àti ìjọba tìtì
- Ìwádìí rèé lórí gbas-gbos tó wáyé lórí ikú ọmọogun òfúrufú l'Oshodi l‘Ọ́jọ́bọ
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Oyo ti fòfin de lílọ àti bíbọ̀ ọkọ̀ láti aago mẹ́fà sí mẹ́ta ọ̀sán nítorí ìdìbò ọ̀la
Oludasilẹ ijọ Winners Chapel ni aloju oju opo ayelujara maa n ṣakoba nla fawọn ọdọ.
O ni lilo oju opo ayelujara lọna aitọ kii jẹ k'awọn ọdọ le kọju mọ ohun ti wọn n ṣe eyi ti yoo pada ṣakoba fún ọjọ ọla wọn.
"Wiwa loju opo ayelujara ni gbogbo igba ti gba akoko lati ronu, awọn mii le ba ọrẹ wọn sọrọ lori ayelujara lati aarọ di alẹ.
Awọn onimọ kan tiẹ sọ pe isọri kan naa ni aloju oju opo ayelujara ati mimu oogun oloro, ọti ati ṣiṣe ṣina jọ wa," Oyedepo ṣalaye.
Biṣọọbu Oyedepo ni wiwa loju opo ayelujara ni gbogbo igba ti gba aye tawọn ọdọ fi le ṣe nkan iyebiye lọwọ wọn.
Pasitọ ijọ Winners sọ pe igbe aye ti ko ba ni afojusun kan gbogii ko ni ìtumọ kankan.
O ni awọn ti wọn ba ni afojusun ibi ti wọn ba n lọ nikan lo le dé ebute ayọ ayanmọ wọn.
Oyedepo ni asiko ti to fawọn ọdọ lati ji giri ki wọn sì ṣiṣẹ lori ọjọ.














