Coronavirus: Ọmọ orílẹ̀-èdè France kan ti kó àrùn Coronavirus wọ Senegal

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Minista eto ilera orilẹ-ede Senegal, Diouf Sarr ti sọ pe arun Coronavirus ti tan de orilẹ-ede naa.
Diouf ni okunrin ọmọ orilẹ-ede France kan to n fi Senegal ṣebugbe lo ko arun naa wọle lẹyin to ṣabẹwo si orilẹ-ede rẹ lọsu Keji.
Okunrin naa pada si Senegal lọjọru to kọja, to si ṣabẹwo si ile iwosan kan lẹyin to ṣaisan rampẹ, ṣugbọn ile iwosan ọhun si fi ọrọ naa to ileeṣẹ eto ilera leti latari ibẹru arunb Coronavirus.
- A dúpẹ́ o! Lẹ́yìn àyẹ̀wò, kò sí alárùn Coronavirus ní Nàíjíríà, sáká lara wa dá - Mínísítà
- Obìnrin tó ń ṣiṣẹ́ ẹrú ní Oman tó bá fẹ́ òmìnira, yóò bá ọ̀gá rẹ̀ ṣùn - obìnrin méjì tó ti oko ẹrú dé
- Ẹ gbọ́ ǹkan ti àwọn òṣèré tíátà sọ nípa Pa Kasumu
- "Àbámọ̀ ló gbẹ̀yìn bí mo ṣe yípadà láti obìnrin sí ọkùnrin, ń kò bá tí ṣe bẹ́ẹ̀"
Lọwọ yii, okunrin ọhun ti wa ni apaọ nile iwosan nibi to ti n gba gba itọju.
Ṣugbọn ijọba Senegal ti bẹrẹ si n wa awọn eeyan ti wọn jọ wọ ọkọ baalu kan naa lati France si Senegal.
Orilẹ-ede Senegal ni orilẹ-ede keji ni iha isale asale Sahara ti arun naa ti wọ bayii lẹyin Naijiria.

Oríṣun àwòrán, @Macky_Sall
- Kaduna tún gbàlejò ìkọlù àwọn agbébọn, àádọ́ta èèyàn míì rọ̀run ọ̀sán gangan
- Ọ́lọ́pàá bá aṣọ, bàtà àti fóónù ọkùnrin tó dàwátì nílé Pásítọ̀ etí òkun l‘Eko
- Ẹ fi ọkàn balẹ̀ lórí àrùn Coronavirus, à ń ṣa ìpa wa láti dènà ìtànkálẹ̀ rẹ̀ - Buhari
- Ẹ́ fún ọmọ Nàíjíríà ní ẹ̀kọ́ tó yè kooro dípò kẹ rán Boko Haram tó ronúpìwàdà lọ kàwé lókè òkun - Serap
Aarẹ ilẹ Senegal, Macky Sall ti rọ awọn eeyan orilẹ-ede naa lati ma gba ibẹru kankan laye ninu ọkan nitori iṣẹlẹ ọhun.
O ni ijọba oun yoo sa ipa rẹ lati ri pe arun naa ko di tọrọ kọbọ lorilẹ-ede ọhun.













