Coronavirus: Ẹ wo ohun tí ààrẹ Buhari sọ lórí aáyan ìjọba láti dènà Coronavirus

Oríṣun àwòrán, @MBuahri
Aarẹ orilẹede Naijiria, Muhammadu Buhari ti kilọ fun awọn Niajiria lati maṣe paya lori aarun Coronavirus to n ja rain nilẹ.
Buhari sọ eyi lasiko to fi atẹjade lede lati ẹnu oluranlọwọ pataki rẹ, Malam Garba Shehu ni lọjọ Aiku.
O ni ibanujẹ ọkan lo jẹ fun oun nipa iroyin pe, Coronavirus ti wọ ipinlẹ Eko lati ọdọ ọmọ ilẹ Italy to wa ṣiṣẹ ni ileeṣẹ Lafarge Cement ni ipinlẹ Ogun.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Buhari,nígbà wò ló fẹ́ bá ọmọ Nàìjíríà sọ̀rọ̀ nípa Coronavirus-PDP
- Oman Returnees: Ọ̀kan lára àwọn obìnrin méjì náà ní òun ṣiṣẹ́ ọdún kan láì mú ₦5 padà wálé
- Ìtàn ayé Taiwo Oredein rèé, àgbà òṣèlú tó parí ayé rẹ̀ sọ́gbà ẹ̀wọ̀n
- Ẹ́ fún ọmọ Nàíjíríà ní ẹ̀kọ́ tó yè kooro dípò kẹ rán Boko Haram tó ronúpìwàdà lọ kàwé lókè òkun - Serap
- Buhari ò, àwáwí rẹ ṣú wa, aáyan ìjọba rẹ̀ mẹ́hẹ lórí ètò ààbò - Ìjọ Aguda figbe ta
Amọ, aarẹ Buhari gboriyin fun ileeṣẹ eto ilera ti ijọba apapọ ati awọn ajọ miran, fun iṣẹ takuntakun ti wọn ṣe lati tete gbogun ti itankalẹ arun naa ni ipinlẹ Eko ati Ogun.

Oríṣun àwòrán, @MBuhari
Aarẹ Buhari wa kesi awọn ọmọ Naijiria ati ẹka ijọba to n risi arun coronavirus naa, lati ri wi pe awọn naa sa ipa wọn lati ma a ṣe akiyesi ayika wọn.
Bakan naa lo kesi wọn lati ri daju wi pe gbogbo aṣẹ ti ajọ to n risi eto ilera lagbaye, WHO pa fun wọn, nipa imọ toto ati fifọ ọwọ nigbakugba ni wọn tẹle.
Saaju ni ẹgbẹ oṣelu alatako lorileede Naijiria, Peoples Democratic Party, ti bẹnu atẹ lu aarẹ Muhamadu Buhari lori bi ko se sọrọ nipa aisan Corona Virus to wọ Naijiria.
Akọwe ipolongo ẹgbẹ naa, Kola Olongbondiyan ni aifini peni, aifeeyan peeyan ni iwa yii jẹ, bi aarẹ ko ti ṣe ti ba awọn ọmọ Naijiria sọrọ.












