Yollywood: Odunlade Adekola, gbajúgbaja òṣèré tí wọ́n ń jẹ ọ̀rọ̀ rẹ̀ lẹ́nu

Odulade Adekola ati Yemi Osinbajo

Oríṣun àwòrán, Odunlade Adekola/Instagram

Àkọlé àwòrán, Adekola jẹ́ òṣèré ọmọ Yorùbá kan tí ọ̀pọ̀ ènìyàn ń bẹ́rí fún lágbo àwọn òṣèré

A bí i ní ọjọ́ kọkànlélọ́gbọ̀n osù kejìlá ọdún 1976. Ọmọ ilu Otun Ekiti, ìpínlẹ̀ Ekiti ni Odunlade.

Òsèré tíátà, olóòtú àti olùdarí eré ní Nàìjíríà ni. Òhun ni alásẹ àti olùdarí ilé isẹ́ fíìmù Odunlade Adekola (OAFP).

Odunlade Adekola

Oríṣun àwòrán, odunomoadekola

Àkọlé fídíò, Ọmọ Yoruba ni mi
Odunlade Adekola

Oríṣun àwòrán, oduomoadekola

Ó bẹ̀rẹ̀ eré tíátà rẹ̀ ní kékeré nípa síse ẹ̀fẹ̀ nínú àwọn ere orí ìtàge ní ìjọ rẹ̀ nígbà náà lọ́hun to si bẹrẹ si ni di gbajugbaja pẹlu ipa rẹ ninu ere "Asiri Gomina wa" lọdun 2003.

Ilu Abeokuta ni ipinlẹ Ogun ni Odunlade Adekola dagba si to si ti lọ ile iwe alakọbẹrẹ to fi mọ ile iwe girama ko to lọ tẹsiwaju nile iwe giga akọṣẹmọṣẹ Moshood Abiola.

Àkọlé fídíò, Ọ̀gá Bello: Àìgbọ́n ló ń da àwọn òsèré tíátà tó ń jà lórí ayélujára láàmú
Odunlade Adekola

Oríṣun àwòrán, odunomoadekola

Odunlade Adekola tun lọ ka iwe kun iwe ni fasiti ilu Eko nibi to ti kawe gboye ninu imọ ẹkọ "Business Administration".

Ọdun 1996 gan ni Adekola bẹrẹ iṣẹ fiimu ṣiṣe nigba to dara pọ mọ ẹgbẹ awọn oṣere ni Naijiria.

Lati igba naa, o ti kopa ninu ọpọlọpọ ere ti ko lonka, oun gan ti kọ ọpọ ere o si ti dari ati ṣe agbejade ọpọlọpọ fiimu.

Odunlade Adekola

Oríṣun àwòrán, odunomoadekola

Odu ni Odunlade Adekola, ọna to si n gba ṣe ipa kipa ti wn ba fun un maa n jẹ ara ọtọ eyi to mu ki awọn eniyan maa pe e ni ọ̀jẹ̀ òṣèré tó mọ iṣẹ́ rẹ̀.

Kii si aṣadanu ninu kiko ipa rẹ ninu ere eyi si ti mu ki awọn to fẹ́ ki o ba wọn ṣe iṣẹ mii tabi gbe iṣe tabi ọja wọn larugẹ n wa a pẹlu ọpọlọpọ owo.

Odunlade Adekola

Oríṣun àwòrán, oduomoadekola

Didi mọlumọọka ti mu ki Odunlade Adekola gba oriṣiriṣi ami ẹyẹ gẹgẹ bi oṣere to dantọ ni oniruuru ọna ninu ere tiata.

Odun o ba a mọ nibi ere ṣiṣe nikan, o tun fi iṣẹ orin kikọ kun un.

Baale ile ni Odunlade Adekola, o gbeyawo, Ọlọrun si fi ọmọ ta igbeyawo rẹ lọrẹ.

Odunlade Adekola

Oríṣun àwòrán, odunomoadekola

Àkọlé fídíò, Éégún tó wà nídí Yoruba Bollywood, Samo Baba f'ojú hàn o!