Coronavirus: Ẹ̀yin tí ẹ lọ ra aṣọ Okirika l'Ọjà Ọba Akure, ẹ lọ ṣàyẹ̀wò àrùn Coronavirus - Akeredolu

Oríṣun àwòrán, @RotimiAkeredolu
Gomina ipinlẹ Ondo, Rotimi Akeredolu ti rọ awọn eeyan to lọ ra aṣọ aloku ni Ọja Oba ilu Akure laipẹ yii lati lọ ṣe ayẹwo arun Coronavirus.
Akeredolu lo ṣo ọrọ naa nigba to n jabọ ibi iṣẹ de duro lori ọrọ Covi-19 ni ipinlẹ ọhun.
Ikede yii lo waye lẹyin ti obinrin kan to ni arun naa sa kuro nile itọju awọn alarun Coronavirus.
Lẹyin ọjọ diẹ ti awọn agbofinro ti n wa obinrin naa ni ọwọ tẹẹ ni Ọja Ọba nibi to ti n ta aṣọ 'Okirika' laarin ilu Akure.
Akeredolu tun sọ loju opo Twitter rẹ pe " A rọ awọn ara ilu to ti lọ ra aṣọ aloku ni Ọja Ọba, nibi ti a ti mu ẹni kẹtalelogoji to ni arun Covid-19 lati pese ara wọn fun ayẹwo ni kia kia."
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Gomina ọhun ni igbesẹ yii ṣe pataki fun anfani ara wọn ati fun gbogbo ara ilu lapapọ.
Lẹyin naa lo kede pe apapọ awọnj to ti ni arun naa ti di mẹtalelogoji bayii.
Ọjà Ọba ní Akure ni ọwọ́ ọloọ́pàá ti tẹ aláàrùn Covid-19 tó sá kúrò ní ilé àyẹ̀wò - Akeredolu

Oríṣun àwòrán, @tasty_cubes
Ọwọ ọlọpaa ti tẹ alaarun Coronavirus to sa kuro nile iwosan to ti n gba iwosan ni Ọja Ọba ni Akure, ni ipinlẹ Ondo
Kọmisọnna fun eto ilẹra, Wahab Adegbenro sọ wi pe alaarun naa to jẹ obinrin ni ayẹwo fihna pe o ni arun Coronavirus ni ipinlẹ Imo amọ to salọ si ipinlẹ Ondo.
Adegbenro ni lẹyin ti obinrin naa salọ ni ijọba ipinlẹ Ondo ati Imo parapọ bẹrẹ si ni wa obinrin naa ki wọn to wa ri.

Oríṣun àwòrán, @RotimiAkeredolu
Wọn ni ibi ti obinrin naa ti n ta aṣọ aloku ni ọwọ ti tẹ ẹ.
Amọ, Kọmisọnna naa koju oro si iru iwa bayii ti o le fa ki aarun naa tankalẹ si.
- A kò tíì lè sọ ti ìfipabánilòpọ̀ àmọ́ òkúta ni wọ́n fi fọ́ orí Azeezat - Ọlọ́pàá Oyo
- Ìyá àádọ́rin ọdún sọ bí ọkùnrin ọdún márùndínlọ́gbọ̀n ṣe fipá bá òun lòpọ̀
- 'Bí Covid19 bá peléke síi l'Eko, ilé la ó ti máa tọ́jú àwọn kan' - Ìjọba ìpínlẹ̀ Eko
- Níbo ni Sẹ́nétọ̀ Abiola Ajimobi, gómìnà àná ní ìpínlẹ̀ Oyo wà?
Bẹẹ ni wọn wa rọ awọn eniyan lati tẹlẹ imọran ijọba lori ofin yiyagofunraẹni ti o le dẹkun itankalẹ arun Coronavirus.
Ti a ko ba gbagbe, Ajọ Amuṣẹya lori aarun Coronavirus ni ipinlẹ Imo lo ke gbajare pe eniyan mẹẹdọgbọn ti sa kuro ni ile ayẹwo aarun Coronavirus ni ipinlẹ Imo.














