Ẹgbẹ́ ìlànà ọmọ Oòdùà fẹ́ wọ́gilé ẹjọ́ tó pè tako ìmúnádóko ìwé òfin Nàìjíríà tọdún 1999 l'Osun

aworan yoruba nation

Oríṣun àwòrán, screenshot

Ẹgbẹ ilana ọmọ Oodua to n ja fun ominira ilẹ Yoruba ti kede pe awọn yoo fa iwe ẹjọ ti awọn pe tako imunadoko iwe ofin Naijiria tọdun 1999 ya niwaju ile ẹjọ giga apapọ to wa nilu Oṣogbo.

Atẹjade kan ti alukoro ẹgbẹ Ilana Ọmọ Oodua lagbaye, Maxwell Adelẹyẹ fi sita lo sọ eyi.

O ṣalaye pe ẹgbẹ naa gbe igbesẹ lati gbe ẹjọ ọhun kuro niwaju ile ẹjọ nilu Osogbo nitori ati lee lọ tun ẹjọ ọhun pe niwaju ile ẹjọ giga apapọ to wa nilu Abuja.

Ati pe niwọn igba to jẹ pe nilu Abuja gan an ni amofin agba orilẹede Naijiria wa.

Atẹjade naa tẹsiwaju pe, amofin Tolu Babalẹyẹ to n ṣaaju ikọ agbẹjọro fun ẹgbẹ Ilana Ọmọ Oodua lagbaye, lo gba ẹgbẹ naa nimọran pe ki wọn fa ẹjọ naa ya.

O ni eyi yoo je ki o kuro niwaju ile ẹjọ to wa nilu Osogbo ki wọn ba le e gbe e lọ si ile ẹjọ giga apapọ lẹkun Abuja.

Ati pe o wa ni ibamu pẹlu ohun ti ẹkun ile ẹjọ naa ni Ado Ekiti sọ lori ibi gan an to yẹ fun gbigbọ ẹjọ ti wọn pe naa.

Ẹgbẹ Ilana Ọmọ Oodua lagbaye to jẹ olupẹjọ lori ẹjọ yii n fẹ ki ile ẹjọ wọgile iwe ofin Naijiria ti ọdun 1999 nitori ni ero wọn, o tako ilana aparo kan ko gaju kan lọ.

Amin idanimọ ẹgbẹ ilana ọmọ oodua

Oríṣun àwòrán, other

Bakan naa ni wọn tun ṣalaye ninu atẹjade ọhun pe wọn yoo daapọ mọ ẹjọ ti wọn pe nilu Ado Ekiti.

Ti wọn yoo si tun wa fi awọn olupẹjọ kun awọn olupẹjọ ti wọn yan sii tẹlẹ

Awọn olupẹjọ tuntun ti wọn fẹ ko mọra lori ẹjọ naa bayii ni awọn ọmọ bibi ipinlẹ Eko, Ogun, Ọyọ, ati Ondo.