You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
2023 Election: Femi Falana ní òfin kò faàyè gba kí Goodluck Jonathan dupò Ààrẹ
Ìdí nìyí tí Jonathan kò fi le díje dupò Ààrẹ Nàìjíríà mọ́
Leyin ti awọn fulani darndaran kan ra fọọmu fun Goodluck Jonathan lati dije dupo aarẹ Naijiria ni awọn eeyan tun ti n beere pe ṣe o lẹtọ lati dije dupo labẹ asia ẹgbẹ APC ni.Èmi ò gbé'ṣẹ́ rán ẹnikẹ́ni láti ra fọ́ọ̀mù ìdíje ààrẹ fún mi o, ẹ máà kóbá mi -Ààrẹ tẹ́lẹ̀ Goodluck Jonathan fún Miyetti Allah lésì
Ni kete ti iroyin naa milẹ titi tan ni Goodluck jade sọ pe oun ko fẹ fọọmu idije dupo aarẹ naa.
- Wo àwọn obìnrin mẹ́wàá tí ipa wọn kò ṣe fọwọ́ rọ́ sẹ́yìn ní ààfin Oyo
- Kọ́ńdọ̀ọ̀mù méjìlá lá rí ní iyàrá ilé ìtura tí wọ́n ti fípa bá arábìnrin Ulochi lòpọ̀- Olọ́pàá
- FIFA ní kí àjọ bọ́ọ̀lù ní Nàìjíríà, NFF ó san N156m owó gbà máà bínú fún Gernot Rohr
- Wo àwọn òjé tí àwọn olóṣèlú máa fi ń jẹ àwọn ènìyàn bí ètò ìdìbò bá ti ń súnmọ́lé
- Báwo ni ọ̀rọ̀ ilé ṣe fa Gbas-gbos láàrín Mercy Aigbe, ìyáále rẹ̀ àti ọkọ rẹ̀?
- Human Rights Watch fẹ̀sùn àìbìkítà kan ìjọba Naijiria lẹ́yìn ikú awọn olùwọ́de lásìkò ìwọ́de EndSARS
Kini o ti kọkọ ṣẹlẹ laarin Goodluck ati Falana?
Gbajúgbajà agbẹjọ́rò àti ajàfẹ́tọ̀ọ́ ọmọnìyàn, Femi Falana ti sọ wí pé Ààrẹ àná orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, Goodluck Jonathan kò le díje dupò Ààrẹ orílẹ̀ èdè yìí mọ́.
Falana nínú àtẹ̀jáde kan tó fi léde ní ọjọ́bọ̀, ọjọ́ Kejìdínlọ́gbọ̀n, ọdún 2022 ní lábẹ́ òfin Jonathan kò le dupò Ààrẹ mọ́ lábẹ́ òfin.
Ó ní wí pé abala kẹtàdínlógójé ìwé òfin orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ti là á kalẹ̀ wí pé ẹnikẹ́ni tí wọ́n bá ti búra wọlé fún gẹ́gẹ́ bí Ààrẹ láti parí sáà Ààrẹ ẹlòmíràn, kò le ṣe ju sáà kan lọ.
- Wo bí ètò Orò Ìje Oba Lamidi Adeyemi to wàjà ṣe lọ ní Oyo
- Ìjàmbá iná tó wáyé kò débi ibojì T. B. Joshua – Ilé ìjọsìn Synagogue
- Ọmọ Ọba Charles kàn sí BBC lórí àjọ̀dún ọdún 90 tí BBC bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìròyín, Oríadé sọ̀rọ̀ pé..
- Ìj̀à tó bẹ́ sílẹ̀ ní Sudan ti gbẹ̀mí ènìyàn 200 lára àwọn tó sá àsálà fún ẹ̀mí wọn kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ ogun Janjaweed
- Iléẹjọ́ sún ìdájọ́ Abba Kyari síwájú, ìgbà wo ni wọ́n n gbée lọ jẹ́jọ́ Hushpuppi ní America ní ọ̀pọ̀ ń béèrè
- Ohun tó yẹ kó mọ nípa ìyípadà òfin tó dé ijinigbe ní Nàìjíríà rèé
- Ìjọba àpapọ̀ kéde ọjọ́ Ajé àti ọjọ́ Ìṣẹ́gun fún ìsinmi ọdún àti àyájọ́ ọjọ́ Òṣìṣẹ́
Ohun tí ó ṣokùnfà ọ̀rọ̀ yìí ni bí awuyewuye ṣe ń lọ lórí pé Ààrẹ àná Goodluck Jonathan yóò darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress (APC) láti dúpò Ààrẹ.
Ó ní ẹgbẹ́ òṣèlú tó bá mú Jonathan gẹ́gẹ́ bí olùdíje ni ó ṣeéṣe kí wọ́n kojú ìjákulẹ̀ nílé ẹjọ́.
Ẹgbẹ́ àwọn ìdàgbàsókè Igbo ní àwọn yóò wọ Jonathan lọ sí ilé ẹjọ́
Bákan náà ni igbákejì alága ẹgbẹ́ ìdàgbàsókè àwọn ẹ̀yà Igbo, Dókítà Law Mefor ní àwọn yóò gbé Jonathan lọ sí ilé ẹjọ́ tí ó bá fi lè kéde wí pé òun fẹ́ dupò Ààrẹ.
Mefor ní bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun gbàgbọ́ wí pé ẹkùn gúúsù ìlà oòrùn orílẹ̀ èdè yìí ló yẹ kí Ààrẹ ti wá lọ́dún 2023, ó ní ìwé òfin orílẹ̀ èdè yìí kò fàyè gba kí Jonathan gbégbá ìbò mọ́.
- Indonesia fòfin de títa epo pupa rẹ̀ sílẹ̀ òkèèrè, wo ipa tí yóò ní lára Naijiria àti Africa lápapọ̀
- Ọwọ́ tẹ ọmọ ológun Nàìjíríà tó ń lẹ̀dí àpò pọ̀ pẹ̀lú ISWAP, wo bí o ṣé gbà ẹ̀mí ará rẹ̀
- Ìgbẹ́jọ́ Ilànà Ọmọ oodua àti Náìjíríà ti bẹ̀rẹ̀ nílé ẹjọ́ ní Ekiti
- Ọ̀pọ̀ ènìyàn ló kú ikú àìtọ́jọ́ nítorí ẹnubodè tíjọba àpapọ̀ tì pa- Àwọn ènìyàn ìlú Idiroko tú pẹrẹpẹ́rẹ̀ ọ̀rọ̀
- Mo ti 'ùnfollow' ẹ lórí 'social media'; Ọlọ́run a ṣe idajọ fún ẹyin méjèèjì- Iyawo Yul-Edochie
Ẹ ó rántí pé ní ọ̀sẹ̀ tó kọjá ni Jonathan ní òun ń kàn sí àwọn ènìyàn òun lọ́wọ́ láti mọ̀ bóyá òun yóò gbégbá ìbò lọ́dún 2023.
Bákan náà ni àwọn àhèsọ ọ̀rọ̀ kan ti ń lọ wí pé Jonathan ti ń fún ẹgbẹ́ òṣèlú APC gbèdéke wí pé tí òun yóò bá darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ òṣèlú náà, wọ́n gbọ́dọ̀ fi òun ṣe olùdíje ipò Ààrẹ.