Guinea : Ìdí tí ìdìtẹ̀ gbàjọba Ààrẹ Alpha Conde ṣe wáyé ní Guniea

Oríṣun àwòrán, Guinea Tv
Awọn ologun ni orilẹ-ede Guinea ti gba ijọba nilẹ naa.
Iditẹgbajọba ti wo ijọba Ààrẹ Alpha Conde lulẹ.
Ọpọ ọmọ orilẹ-ede Guinea ni inu wọn kò dùn sí ijọba Aarẹ Conde lẹyin to wọlé fun saa kẹta ní bii ọdún kan din diẹ sẹyin.
- Kò sí aburú bí àwọn kàn ṣé n béèrè fún ìdásílẹ̀ Yorúbá Nation ṣùgbọ́n...
- Bí àṣìta ìbọn ṣe pa ọmọ ọdún 9 níbi ètò ìdìbò ìjọba ìbílẹ̀ ní Kaduna
- Ògo ilé wá wọlẹ̀ lójijì! àwọn darandaran ajínigbé pa abúrò mí! - Ọmọyẹle Ṣowore
- Ìjọba dá àwọn Kristẹni tó ń rìnrìnàjò lọ sí Isreal padà nítorí abẹ́rẹ́ ajẹsára Covid-19
Rogbodiyan bẹ sílẹ lẹyin ti Conde wọle tan, ẹgbẹ alatako naa kọju ìjà sí ijọba Conde.
Ile iṣẹ ologun gbe Conde, ẹni ọdun mẹtalelọgọrin sí àhámọ́ lẹyin ti awọn eeyan gburo ibọn lẹgbẹ ile iṣẹ aarẹ ni Conakry.
Ọgagun GFS, Mahamady Doumbouya lo Kede lori ẹrọ amohunmaworan le awọn ologun ti gba ijọba.
Ọgagun Doumbouya ṣèlérí pé àwọn ologun yóò ṣètò lati gbe ijọba fún alágbádá.
O ni omi tuntun ti ri, ẹja tuntun Si ti wọọ lori ìṣèjọba orilẹ-ede Guinea bayii.
Ajọ AU, UN ati ECOWAS naa ti bu ẹnu atẹ lu igbesẹ awọn ologun ni Guinea.
Awọn yii fẹ ri pe awọn ologun gbe ijọba padà fún alágbádá ni kiakia.















