Central Bank Nigeria bans BDCs: Wo ìdí tí báǹkì àpapọ̀ Nàìjíríà CBN fi tilẹ̀kùn mọ́ àwọn tó ń sẹ owó dọ́là, pọ́ùn ní Nàìjíríà

Oríṣun àwòrán, other
Banki apapọ orilẹede Naijiria ti gbẹsẹle tita awọn owo ilẹ okeere fun awọn olokoowo paṣipaarọ owo ilẹ okeere ti ọpọ mọ si Bureau de Change ni Naijiria.
Godwin Emefiele to jẹ gomina agba banki apaps Naijiria lo kede eyi ninu ifọrọwerọ kan pẹlu awọn oniroyin lẹyin ipade igbimọ kokaari lori ilana iṣuna.
- Wọ́n ti fi ẹ̀sùn míì kan Sunday Igboho ní ìlú Benin! - Agbẹ́jọ́rò Igboho
- Iléẹjọ́ sún ìgbẹ́jọ́ Baba Ijesha di oṣu kẹ́jọ lẹ́yìn tí wọ́n fọ̀rọ̀ wá ọmọ́débìnrin tọ́rọ̀ kàn lẹ́nuwò
- Ẹ gbé Sunday Igboho kúrò láhàmọ́ ọlọ́pàá wá sí ibi ìpamọ́ mìí ní Cotonou títí tí... - Adájọ́
- A dúpẹ́ kò sí ọmọ ilé ẹ̀kọ́ Bethel Baptist School tí wọ́n fipa bá lòpọ̀ nígbèkùn ajínígbé - Ààrẹ Baptist
O ni iye owo dọla amẹrika ti wọn n ya sọtọ fun awọn olokoowo ṣiṣẹ owo ilẹ okeere naa ko lee yọ mọ.
Emefiele tun ṣalaye pe awọn olokoowo ṣiṣẹ owo ilẹ okeere naa ti sọ ara wọn di ọpa ipọnwo kotọ lorilẹede Naijiria. O ni wọn ti kọ ẹyin si ojuṣe wọn, wọn si ti sọ ara wọn di agbodegba iwa jibiti ati ikowojẹ lorilẹede Naijiria.
Bakan naa lo ni ko si aaye fun iforukọsilẹ awọn olokoowo ṣiṣẹ owo ilẹ okeere tuntun bayi ati pe awọn banki ni yoo maa ṣe ojuṣe ṣiṣẹ owo ilẹ okeere bayii.
O ni awọn banki yoo ni ẹka lawọn banki wọn lati maa ṣẹ owo ilẹ okeere fun araalu.









