Bethel Baptist Kidnap Rev. Israel Akanji: Àdúrà wa láì sinmi ló dá sí títú àwọn ọmọ ilé ẹ̀kọ́ Bethel Baptist nígbèkùn ajínígbé

Oríṣun àwòrán, NIGERIA BAPTIST CONVENTION
Ààrẹ apapọ ijọ Onitẹbomi ni Naijiria (Nigeria Baptist Convention), Israel Akanji ni ìjọ Baptist jákejádò orílẹ̀-èdè mẹ́rìndíláàdọ́jọ ló ń gbàdúrà fún àwọn ọmọ tí àwọn ajínígbé jí lásìkò tí wọ́n wà ni ìgbèkùn.
Ààrẹ náà ní àdúrà láì simi yìí ló ṣe àwárí àwọn èyí tó padà wálé.
Akanji sọ pé bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé lóòtọ́ ni àwọn ń gbé òunjẹ lọ fun wọ́n ní àwọn ibi ti wọ́n bá pa láṣẹ pé kí àwọn gbé òunjẹ wá gẹ́gẹ́ bí wọ́n ba ṣe paa láṣẹ.
- A ń gbóhùn àdúrà sókè ní orílẹ̀èdè 127 lágbàáyé torí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Baptist tí wọ́n jígbé ní Kaduna -Baptist Convention
- Wo àǹfàní tí wọ́n ṣẹ̀sẹ̀ fún ìyàwó Sunday Igboho ní Cotonou
- Kí ló mú kí ìjọba ìpínlẹ̀ Eko fẹ́ kí adájọ́ fòfin de Yomi Fabiyi nílé ẹjọ́?
- Ẹ gbé Sunday Igboho kúrò láhàmọ́ ọlọ́pàá wá sí ibi ìpamọ́ mìí ní Cotonou títí tí... - Adájọ́
- Wọ́n ti fi ẹ̀sùn míì kan Sunday Igboho ní ìlú Benin! - Agbẹ́jọ́rò Igboho
O ní ìjọ Baptist kò san owó ìtúsílẹ̀ gún àwọn ajínigbé sùgbọ́n òun kò le sọ nǹkan ti àwọn òbí àti àwọn tí ọ̀rọ̀ náà kan ṣe.
Ọmọ mọkanlélọ́gọ́fà ni wọ́n jí gbé lóòtọ́ ṣùgbọ́n lẹ́yìn tí wọ́n tú àwọn méjìdílọ́gbọ̀n kalẹ̀, wọ́n tún padà fí àwọn mẹ́rìn mííràn sílẹ̀.
"Gbogbo ọmọ tí a ti ri báyìí ti pé méjìdínlógójì nítorí yàtọ̀ sí àwọn ọmọ yìí a tún rí àwọn ènìyàn mẹ́rin mííràn tí wọ́n fi sílẹ̀.
Ní báyìí ó ku ọmọ mẹ́tàlélọ́gọ́rin ló kù láhàmọ̀ àwọn ajínigbé"A dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run pe kò sí ọmọ tí wọ́n fi ipá bá lòpọ̀ nínú wọn nítorí pé olórí wọn ti kìlọ̀ pé wọn kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ kan énikẹni ninu àwọn ọmọ náà.Ẹ̀wẹ̀, ààrẹ náà ní láti ọjọ́ tí wọ́n ti jí àwọn ọmọ náà gbé, wọn kò wẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò pààrọ̀ asọ wọn, bákan náà ni wọ́n gbàwọn laáyè láti máa ṣe ìpàdé àdúrà wọn láràrọ́ọ̀.
A sì ń kó ìròyìn yìí jọ lọ́wọ́













