Africa Eye: Ahmed Isah rèé tíí ṣe ààrẹ lásán làsàn ní Nàíjíríà tí inú aráàlú dùn sí
Lojoojumọ ni Ahmed Isah, tii se olootu eto Bẹrẹkẹtẹ maa n ya awọn ọmọ Naijiria lẹnu pẹlu sna to n gba lati gba ẹtọ wọn le wọn lọwọ.
Ọna to n gba lati fidi ẹtọ ọmọniyan le wọn lọwọ yii ni eto rẹ naa to n se lori redio ati tẹlifisan, ti ọpọ eeyan maa n wo.
Ahmed, ti ọpọ eeyan mọ si ‘Ordinary President’, taa mọ si aarẹ lasan lasan ni ọpọ ọmọ Naijiria sọ di orisa nitori bo se n lo agbara rẹ lati gba ẹtọ mẹkunnu fun wọn.
- "Shrine" ni wọ́n ń pé ọ́fíísì wa táa ti ń sanwó òṣìṣẹ́fẹ̀yìntì", BBC Africa Eye tú àṣírí wọn
- Àkàrà tú sépo! Ikọ̀ ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ BBC tú àṣírí bí SARS ṣe ń fìyà jẹ aráàlú
- Bí ìròyìn BBC nípa oògùn ikọ́ Codeine ṣe ń tún ayé tó ti bàjẹ́ ṣe
- 'Kìí ṣe àròsọ, mo ní fọ́nrán fídíò àwọn ẹlẹyẹ ìlú mi'
- Wo ìgbé àyé ìyá àti ọmọbìnrin rẹ̀ tó ń fi iṣẹ́ aṣẹ́wó jẹun
- Àṣírí tú! Olùkọ́ fásitì méjì ń bèèrè ìbálòpọ̀ lọ́wọ́ akẹ́kọ̀ọ́ fún máákì
- Ẹ wá wo igi tó n ṣẹ̀jẹ̀
- Àṣírí tú, è wọ àwọn dókítà tó ń ta ayédèrú oògùn Coronavirus
Se lo maa n pe awọn oloselu nija lori afẹfẹ, to fi mọ ileesẹ ọlọpaa to maa n gbe wa siwaju awọn ọmọ Naijiria, eyi si mu ki ọpọ mẹkunnu nifẹ rẹ.
Akọroyin fun ẹka iroyin ọtẹlẹmuyẹ nilẹ Afirika, BBC Africa Eye, eyiun Peter Nkanga tọpinpin Ahmed Isah ati ikọ rẹ fun ọpọlọpọ ọsẹ.
Nibẹ si ni wọn ti sawari rẹ pe lootọ lo le jẹ aarẹ lasan lasan to n yi igbe aye ọpọ eeyan si rere amọ awọn ọna to n gba eyi to n mu awuyewuye lọwọ le mu ewu miran dani.




