Buhari driver: Kò sẹ́ni tó lè ní kí Buhari má gba ìtọ́jú nílẹ̀ òkèèrè - Amúgbálẹ́egbẹ́ Ààrẹ

Oríṣun àwòrán, Femi Adesina
Amugbalẹgbẹ Aarẹ Muhammadu Buhari lori oju opo ikansiraẹni lori ayelujara, Lauretta Onochie ti sọ pe Aarẹ lẹtọọ lati maa lọ gba itọju loke okun.
Onochie lo sọrọ naa ninu atẹjade kan loju opo Twitter rẹ lasiko to n fesi si bi awọn ọmọ Naijiria kan ṣe n bu ẹnu ẹtẹ lu Aare Buahri pe o lọ gba itọju loke okun lasiko ti awọn dokita daṣẹsilẹ ni Naijiria.
Ṣaaju ni ọpọ ọmọ Naijiria ti kọkọ bu ẹnu atẹ lu Buhari pe idi ti ko ṣe le gba itọju ni Naijiria ni pe o kọ lati tun ẹka eto ilera ṣe, koda awọn kan ṣe ifẹhonuhan niluu London pẹlu.
- Sotayo Gaga bẹ́ "speaker" ọdún tó ti ṣegbéyàwó àti ohuin tó fi pamọ́
- Owó àti dúkìá Dongote, Adenuga àti Rabiu tún yarọ síi pẹ̀lú $5.7bn- Forbes
- Ẹ padà wá o ẹ̀yin ẹlẹ́wọ̀n, ẹni tó bá wá wọ́ọ́rọ́wọ́ yóò rí ìdáríjì, ẹni tí kò bá wá ... - Aregbesola
- Tinubu ló lè ṣeé lọ́dún 2023, Pa Fasoranti àti Oba Osemawe Ondo sọ̀rọ̀ sókè
- Wo àwọn Ọ̀gá Àgbà Ọlọ́pàá tó ti jẹ́ látọdún 1999
Lẹyin to de sile ijọba niluu London lawọn eeyan kan ti bẹrẹ ifẹhonuhan, ti wọn si n sọ pe ko pada si Naijiria lati tunṣẹ.
Nigba to n da si ọrọ naa, Onochie sọ pe ko sẹni to le ni ki Buhari ma kan si awọn dokita to n ti n ṣetọju rẹ lati nnkan bii ogoji ọdun sẹyin.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 1
O ni "Aarẹ Buhari yoo tun lọ ṣe ayẹwo miran loke okun to ba di ọdun to n bọ, awọn eeyan yoo si tun pariwo ẹnu lasan naa ni."
"O lọ fun ayẹwo lọdun 2017, 2018, 2019 ati 2020 ki Corona to de, ariwo ẹnu yii kan naa lawọn pa nigba naa."

Oríṣun àwòrán, Lauretta Onochie
Amugbalẹgbẹ Aarẹ naa fi kun pe ko si ọkunri ti yoo gba ki gẹrigẹ miran gẹ irun fun oun nitori gẹrigẹri rẹ ko si ni tosi.
Lauretta fi kun pe "to ba wu Aarẹ lati lọ fun ayẹwo miran lọdun 2022 ati 2023, yoo lọ nitori ọwọ rẹ lo wa."
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 2
Onochie pari ọrọ rẹ pe kaakiri agbaye lawọn eeyan ti maa n tẹkọ leti lati lọ ṣayẹwo lọdọ awọn dokita wọn, nitori naa, ariwo lasan lawọn eeyan n pa, ati pe ariwo naa ko le di Aarẹ lọwọ lati ri olutọju rẹ.
- Àwọn agbébọn tún dáná sun àgọ́ ọlọ́pàá ní Imo, wọ́n tú àwọn tó wà ní àhámọ́ sílẹ̀
- Àrà kìí tán nílé alárà! Aláboyún oṣù mẹ́jọ, Aminat Idris borí nínú ìdíje Taekwondo
- Àwọn nkan tó yẹ kí o mọ̀ nípa adelé Ọ̀gá Àgbà ọlọ́pàá ti Buhari ṣẹ̀ṣẹ̀ yàn
- Mo ti padà sí ẹ̀sìn òwúrọ̀ mi o! Ẹ̀ gbé Ọlọ́run tóbi - Yomi Fabiyi














