Yomi Fabiyi: Fíìmù ‘Owó orí ẹlẹ́wọ̀n’ jẹ́ ká mọ̀ pé ìgbà ìpọ́njú làá mọ ọ̀rẹ́

Àkọlé fídíò, Yomi Fabiyi: Fíìmù ‘Owó orí ẹlẹ́wọ̀n’ jẹ́ ká mọ̀ pé ìgbà ìpọ́njú làá mọ ọ̀rẹ́

Yoruba ni ọwọ epo ni ọmọ araye n ba ni la, wọn kii ba ni la ọwọ ẹjẹ.

Ẹkunrẹrẹ alaye nipa owe yii lo wa ninu sinima tuntun ti Yomi Fabiyi n ya lọwọ, to pe akọle rẹ ni ‘Owo Ori Ẹlẹwọn,”

Nigba ti BBC Yoruba kan si ibi to ti n ya sinima naa, ọpọ awọn akikanju osere la ba ni oko ere naa, ti wsn n sisẹ karakara. Yatọ si Yomi Fabiyi to ni ere, a tun ri Muka Ray, Ronke Odusanya, Adekola Tijani ati bẹẹ bẹẹ lọ.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Nigba to n sọ nipa sinima naa, Yomi Fabiyi ni sinima Owo ori ẹlẹwọn lo n sọ fun wa pe ka mase gbe ara le ọrẹ lasiko ti nnkan n dun fun wa.

O ni igba ipọnju laa mọ ọrẹ, bi oorun si tilẹ mu to, sanmọ dudu diẹ yoo wa.