Plateau runaway girl: to Ekiti: Kíni ó lè mú kí ọmọbìnrin sá kúrò nílé láti ìpínlẹ̀ Plateau lọ sí Ekiti?

omo fi iwe aworancovid 19 boju

Ẹ wo ọmọbinrin to sakuro nile nitori Baba rẹ fẹ fi fun ọkọ tipatipa

Ọmọ ọdun marundinlogun sa kuro ni Plateau wa si Ekiti nitori igbeyawo tipatipa.

Arabinrin ọmọ ọdun marundinlogun ti fi ẹjọ baba rẹ sun lori ẹsun pe baba oun fẹ fi tipatipa fi oun fun ọkọ

Iroyin ni wi pe ọmọbinrin naa kuro ni ile rẹ ni ipinlẹ Plateau wa si ilu Ekiti lati duro ti ẹgbọn rẹ lẹyin to tako igbeyawo tipatipa ti wọn fẹ ṣe fun un.

Eka ajọ awọn agbẹjọro to jẹ obinrin lagbaye, FIDA to wa ni ipinlẹ Ekiti lo fi iroyin naa lede fun awọn akọ̀royin.

Àkọlé fídíò, SS3 ní mo wà báyìí, mo sì ti gba àmì ẹ̀yẹ̀ púpò nílé-lóko gẹ́gẹ́ bí onílù - Ayansike

Alaga Ajọ FIDA, Abilekọ Toyin Odunayo sọ wi pe awọn kọkọ pese ibugbe fun arabinrin naa nigba ti o kọkọ de si ipinlẹ Ekiti, ti ko i tii ri ẹgbọn rẹ ọkunrin to wa ba a.

'Ni igba ti a ri ẹgbọn rẹ, Hameed Adamu sọ wi pe lootọ ni baba rẹ fẹ fi fun ọkọ tipatipa.'

Àkọlé fídíò, Ìṣẹ̀lẹ̀ Kàyéèfì: Ìpáǹle tú Abass Owonikoko sí ìhòòhò ayé, kó tó gba kéú lọ́gbà ẹ̀wọ̀n

Alaga naa salaye pe: 'Adamu ni baba oun ti fi panpẹ ọlọpaa mu arakunrin kan ni Plateau ti wọn fi ẹsun kan wi pe oun lo fun ọmọbinrin naa ni owo lati tẹ ọkọ leti wa si Ekiti.'

'Amọ, ọjọ keji ni wọn fi ọkunrin naa silẹ, amọ baba mi ti sọ wi pe dandan ni oun yoo tun fi panpẹ ọba mu ọkunrin naa lẹẹkeji.'

Ajọ FIDA fikun pe awọn ti gbe ẹjọ naa lọ si ajọ to n risi ẹtọ ọmọniyan lorilẹede Naijiria lati da si ọrọ naa lati ẹka wọn to wa ni ipinlẹ Plateau.

Bakan naa ni Alaga ajọ FIDA naa wa rọ awọn araalu lati ma a ran ara wọn lọwọ, ki wọn si ma a tu asiri awọn eniyan ti wọn ba n fiya jẹ ọmọnikeji wọn ni ọna kọna.

Àkọlé fídíò, Akomolede ati Aṣa lori BBC: Kí ní ìtúmọ̀ Sílébù àti àmi ohun tó ń fún ni?