EKIFEST: kí làwọn ohun tó fakọyọ níbi àjọ̀dún àṣà nípínlẹ̀ Ekiti, EKIFEST tọdún 2019
Ipinlẹ Ekiti ni aṣa ati iṣe ilẹ Yoruba paapaa awọn to nii ṣe pẹlu awọn eeyan ilẹ Ekiti ko ni parun. Idi niyi ti ayẹyẹ ajọdun aṣa fi waye nibẹ.
Ayẹyẹ ajọdun aṣa ipinlẹ Ekiti ti wọn da pe ni EKIFEST n waye lọwọlọwọ bayii ni ilu Ado Ekiti tii ṣe olu ilu Ipìnlẹ Ekiti. Awọn ẹgbẹjẹgbẹ ati ọgba ni wọn ti peju sibẹ lati Ọjọru ti ayẹyẹ naa ti bẹrẹ.
- 'IBB tẹ ń pariwo pé ó kú, kò kú o, Ko ko ko lara ọta ń le! - Agbẹnusọ Kassim
- Ìlé ẹjọ́ rọ Obalufe ti Ile Ife lóyè, wọ́n pàṣẹ́ fún Ọọ̀ni Adeyeye
- Kìí ṣe ìwà ọ̀lẹ ni bàwọn obìnrin ayé òde òní kìí ṣe dàra pọ̀ mọ àwọn olobinrin ilé
- Naira Marley gba ipò mọ́ Atiku lọ́wọ́ gẹ́gẹ́ bí èèyàn tí wọ́n ń wá jùlọ ní Google lọ́dún 2019
- Aisha Buhari figbe ta,o ní pé Garba Sheu tí gbàbọde
- Ọkùnrin tó yí orúkọ padà sí Muhammadu Buhari ṣ'ayẹyẹ ìsọmọlórúkọ ní Kano
Lara awọn manigbagbe ohun to waye lasiko iṣide ayẹyẹ ajọdun aṣa naa lọjọru ni ayẹyẹ afihan awọn ẹgbẹ aṣa gbogbo lati gbogbo ijọba ibilẹ mẹrindinlogun to wa nibi ayẹyẹ naa. Bakan naa lawọn oṣere tiata Yoruba ati ede oyinbo ko gbẹyin nibẹ.

Oríṣun àwòrán, Sunkanmi
Ẹwẹ awọn ẹgbẹ gbogbo lati awọn ẹya ede miran pẹlu wa nibẹ ti awọn olorin si n fi alujo to ba igba mu da awọn to wa nibẹ laraya.

Ninu ọrọ rẹ, Gomina Kayọde Fayẹmi to ṣide ajọdun ọhun tẹnumọ ipinnu iṣejọba rẹ lati tubọ ya owo sọts fun igbelekeẹka aṣa ati iṣe fun idagbasoke ọrọ aje awọn eeyan ipinlẹ Ekiti.
Ni ọjọ Ẹti ni aṣekagba ajọdun naa yoo balẹ ni ilu Ado Ekiti.











