Fake news: ìmọ̀ràn fáwọn ọmọ Nàìríjíà ṣaájú pínpín ìròyìn- Aṣòfin àgbà

Oríṣun àwòrán, others
Igbesẹ ijọba apapọ lati dẹkun bi awọn eeyan ṣe n gbe iroyin ẹlẹjẹ kiri lori itakun ayelujara ko buru, ṣugbọn, o ku nibọn n ro.
Dayo Akinlaja to jẹ agbẹjọrọ agba ati kọmiṣọna fun eto igbẹjọ nipinlẹ Ekiti tẹlẹ lo sọ ọrọ naa ninu ifọrẹowerọ pẹlu BBC lori koko ọrọ yii.
Ni ibẹrẹ ọsẹ yii ni ile igbimọ aṣofin agba l'Abuja gunle abadofin kan, ti yoo ṣe iṣakoso bi awọn ọmọ Naijiria ṣe n lo awọn opo ikansiraẹni lori itakun agbaye.
Erongba awọn aṣofin naa ni lati dẹkun bi awọn eeyan ṣe n pin iroyin ẹlẹjẹ kiri lori itakun agbaye.
Aṣofin agba Akinlaja sọ pe "O yẹ ki ijọba gbiyanju lati dẹkun awọn to ba n sọrọ to le da Naijiria ru lori ẹrọ ayelujara, sugbọn ijọba ko gbọdọ fi ẹtọ ara ilu lati sọrọ dun wọn."

Oríṣun àwòrán, others
Akinlaja ni "ọmọ Naijiria lẹtọ lati sọrọ, sugbọn o yẹ ki wọn sọra fun ọrọ to lee ṣe ijamba fun alaafia ilu."
Akinlaja gba awọn ọmọ Naijiria lamọran lati ṣe iwadii iroyin ti wọn ba gbọ ki wọn to gbe iru iroyin bẹẹ sori itakun agbaye, paapaa iroyin to lee ba elomiran lorukọ jẹ, ati eyi to le da ilu ru.
Oluwatosin Ajibade, ti ọpọ eeyan mọ si "OloriSuperGal" sọ fun BBC pe, yoo sọro funn ijọba lati mu awọn to ba n pin iroyin ẹlẹjẹ kiri lori ẹrọmibanisọrọ wọn.
Ajibade pari ọrọ rẹ pe, ojuṣe gbogbo ọmọ Naijiria ni lati ri pe wọn ṣe iwaadi iroyin ti wọn ba gbọ lati ri daju pe ojulowo ni, ki wọn to pin kaakiri.
- Ọ̀gẹ̀dẹ̀ ń bàjẹ́..; Akẹ́kọ̀ọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ 12 gbà èèyàn láti kọ ìdánwò fún wọ́n
- Òògùn tọ́jọ́ fẹ́ lọ lórí wọn ni àjọ SACA ń rà lábẹ́ àkóso aya Ajimobi - Seyi Makinde
- Ó ṣe jẹ́ ṣọ́ọ́bù aláṣọ kanṣoṣo ni iná tí maa ń ṣẹ́yọ lọdọọ́dún lọ́jà Balogun?
- Bí alárùn Ebola bá wọ Nàíjíríà, kò sí gìrì, a ti múra sílẹ̀ láti paná rẹ̀ - Àjọ NCDC















