Exam Malpractices: Fọ́tò inú káàdì ìdánimọ̀ ló mú kí àkàrà tú sépo

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Aye n bajẹ ọmọ ole n kajọ. Ki ni ka ti ṣe iru eyi si, nigba tawọn akẹkọọ ile iwe alakọbẹrẹ ba n gba eeyan kọ idanwo wọn?
Bẹẹ lawọn eeyan n ṣemọ bi iroyin ti ṣe kan pe, ọwọ ọlọpaa tẹ awọn akẹkọ ile iwe alakọbẹrẹ mejila, ti wọn gba eeyan lati ba wọn joko ṣe idanwo aṣekagba wọn.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- 'Ǹkan tó jẹ́ kí iṣẹ́ ọ̀nà tèmi yàtọ̀ lágbàáyé ni ǹkan tí mò ń lò'
- Òògùn tọ́jọ́ fẹ́ lọ lórí wọn ni àjọ SACA ń rà lábẹ́ àkóso aya Ajimobi - Seyi Makinde
- Ó ṣe jẹ́ ṣọ́ọ́bù aláṣọ kanṣoṣo ni iná tí maa ń ṣẹ́yọ lọdọọ́dún lọ́jà Balogun?
- Osinbajo kìí ṣe amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ Buhari tí yóò máa gbé ìwé lọ fun ní London - Akin Alabi
Iroyin ta gbọ ni pe, awọn akẹkọ lati ile ẹkọ alakọbẹrẹ Sese Bugolo gba awọn akẹkọ naa lati ile ẹkọ girama to wa ni agbegbe Buike ati Mukono ni orilẹede Uganda, lati ba wọn kọ idanwo.
Ọga agba feto ẹkọ lagbegbe naa, Hassan Nkutu ṣalaye lọjọ Iṣẹgun pe, n ṣe laṣiri awọn akẹkọọ naa tu nigba tawọn ri pe aworan ori iwe idanimọ wọn ko papọ mọ ti awọn to n kọ idanwo.

Oríṣun àwòrán, Other
Hassan sọ pe ''ọkan lara awọn ọtẹlẹmuyẹ ta ni ko mojuto idanwo naa lo ri awọn afunrasi ohun. N ṣe la ri pe aworan to wa lori kaadi idanimọ wọn ko papọ mọ eleyi ti ile iṣẹ eto ẹkọ Uganda pese''
Agbẹnusọ ọlọpaa lagbegbe naa, Hellen Butoto sọ pe awọn yoo kesi awọn adari ile iwe naa lati wa ṣalaye ohun to ṣẹlẹ.
- Òògùn tọ́jọ́ fẹ́ lọ lórí wọn ni àjọ SACA ń rà lábẹ́ àkóso aya Ajimobi - Seyi Makinde
- Ó ṣe jẹ́ ṣọ́ọ́bù aláṣọ kanṣoṣo ni iná tí maa ń ṣẹ́yọ lọdọọ́dún lọ́jà Balogun?
- Bí alárùn Ebola bá wọ Nàíjíríà, kò sí gìrì, a ti múra sílẹ̀ láti paná rẹ̀ - Àjọ NCDC
- Olujinmi ló borí ìbò fẹ́kùn gúúṣù Ekiti, Adeyeye gba ile lọ - Iléejọ́ Kòtẹ́milọ́rùn ṣèdájọ́









