London Bicycle ride to Lagos: Ọmọ Naijiria kan ti bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò láti London wá sí Naijiria pẹ̀lú kẹ̀kẹ̀

Kunle Adeyanju

Oríṣun àwòrán, @lionheart1759

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

Adeyanju ni nitori ati pa owo jọ fun itọrẹaanu awọn alaini ni oun ṣe gbe igbesẹ naa.

Irinajo lati ilu Ọba wa si ilu Eko yoo gba arakunrin naa ni ọjọ marundinlọ̣gbọn.

Bakan naa ni yoo gba orilẹede Faranse, Spain, Gibraltae, Morocco, Iwọ oorun agbegbe Sahara, Mauritana,Senegal, Gambia, Mali, Ivory Coast, Ghana, Togo ati Benin ki wọn to wa kọja si Naijiria.

Àkọlé fídíò, Ọdún 20 ni ìran ti jáde pé kí n di ààrẹ!'Wàláhì láàrín ọdún kan péré tí mo bá dé Aso Rock, ẹ wo ǹkan tí ...'

Adeyanju ni owo naa ti oun ba ri tujọ lasiko irinajo oun naa ni yoo lo lati ṣe iranwọ fun ẹka ilera, ipese omi ati ayika mimọ toni toni.

Skip X post
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post

''Ni oni Ọjọ kọkandinlogun ni mo bẹrẹ irinajo lọ si ilu Eko lati ilu Ọba''

Àkọlé fídíò, 'Fásitì Nàìjíríà kò gbà mi wọlé ló mú mi sá lọ Ukraine, àmọ́ ohun tí ojú mi rí nínú ogun náà rèé kí ń tó sá wá Nàìjíríà'

''Ọjọ marundinlọgbọn ni o ṣeeṣe ki n lọ lati fi rin irinajo naa to le ni ẹgberun kilomita ẹgbẹrun lọna mejila.''

Lara awọn ololufẹ rẹ to kii fun iwa akinkanju loju opo Twitter naa ni awọn n gbero lati ṣe iru rẹ.

Wọn wa gbadura fun un lati rin irinajo naa laisi ewu abi ijamba ni gbogbo ibi ti o ba n de.Arakunrin ọmọ Naijiria, Kunle Adeyanju ti bẹrẹ igbesẹ lati rin irinajo pẹlu ọkada rẹ lati ilu Ọba wa si ilu Eko.

Àkọlé fídíò, Female Carpenter: Fatia Garu ní ọ̀pọ̀ èèyàn ni kìí gbàgbọ́ pé obìnrin ló ń ṣiṣẹ́ Káfíńtà