Buhari's visit to Lagos: Wo ẹnu ibodè ìrìnà òfurufú tí Ààrẹ Buhari ń bọ̀ wá ṣèfilọ́ọ́lẹ̀ ní Eko lónìí

Papakọ ofurufu Murtala Muhammed

Aarẹ Muhammadu Buhari ti balẹ bagẹ si ipinlẹ Eko fun awọn akanṣe iṣẹ.

Ikini ni ifilọlẹ ẹnu ibode irina ofurufu tuntun ni papakọ ofurufu Murtala Muhammed ni Eko.

Papakọ ofurufu Murtala Muhammed

Bakan naa ni Aarẹ yoo tun ṣe ayẹwo irinṣẹ nla fun ajilẹ eyi ti ileeṣẹ Dangote ṣe agbekalẹ rẹ.

Irinṣẹ ajilẹ nla

Oríṣun àwòrán, Presidency

Lafikun, iroyin sọ pe Aarẹ buhari yoo yọju si ibi iṣẹ to n lọ lọwọ ni ibudokọ oju omi kan ni agbegbe Lekki nipinlẹ Eko.

Ibudoko oju omi okun to jin ju ni Lekki

Oríṣun àwòrán, Presidency

Àkọlé fídíò, Ẹ má fún mi l'ówó bárà, mò ń bọ́ ẹnu púpọ̀, aya àtọmọ mẹ́ta - Oladapo Okalawon Shonde

Bi wọn ba pari iṣẹ yii, ohun ni yoo jẹ ibudo oju omi okun to jin ju ni Naijiria bakan naa wọn n woye pe ohun ni yoo jẹ ibudo oju omi to jẹ ti igbalode ju lọ ni Iwọ Oorun Afirika.

Papakọ ofurufu Murtala Muhammed

Igba ti Aarẹ Buhari ṣe ibwo si ipinlẹ Eko gbẹyin ni ọjọ Kẹsan oṣu Kejila ọdun 2021 nigba to ṣe ifilọlẹ awọn iṣẹ akanṣe kan ni ileeṣẹ ogun oju omi ni Naijiria.

Nibayii, alakalẹ ti wa fun awon oju ona popo mii ti awon eeyan le gba lati yago fun sunkẹrẹ-fakẹrẹ ọkọ.

Papakọ ofurufu Murtala Muhammed