Olólùfẹ́ méjì lẹ̀pọ̀ lásìkò tí wọ́n n bá ara wọn sùn nínú adágún odò

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ere ifẹ di ere ẹkun fun ọkunrin ati obinrin kan to jẹ ololufẹ , lasiko ti wọn n ni ibalopọ ninu adagun odo.
Ololufẹ meji ọhun ni iroyin sọ pe wọn n wẹ ninu odo Bosomtwi, ni ẹkun Ashanti, lorilẹ-ede Ghana, ti wọn si tun pinnu lati gbadun ara wọn si i, nipa ibalopọ ninu odo naa.
Nibi ti wọn ti n gbadun ara wọn lọwọ, ni wọn ti lẹpọ.
Ere ni, awada ni. Afi bi ẹni pe 'oluwẹri to wa ninu odo naa n binu si wọn pe wọn ri oun fin pẹlu ibalopọ wọn'.
Gbogbo igbiyanju wọn lati tuka lo ja si ofo, eyi to mu ki wọn o bẹrẹ si ni pariwo ẹ gba wa o, ẹ gba wa o.
- Ọ̀nà àbáyọ márùn ún rèé tí obìnrin àti ọkùnrin bá lẹ̀pọ̀ lásìkò ìbálòpọ̀
- Wo bí ìbálòpọ̀ tó gbóná giri-giri ṣe le ran tọkọtaya lọ́wọ́ láti kojú ìpèníjà
- Agbẹnusọ àjọ EFCC Wilson Uwujaren ti ṣàlàyé nǹkan tí ó ṣẹlẹ̀ sí ọ̀gá àjọ náà lósàn ọjọ́bọ
- Wo ìdí méje tí olólùfẹ́ rẹ fi le kọ ìbálòpọ̀ pẹ̀lú rẹ
- Judasi ìran Oduduwa ni Femi Fani-Kayode pẹ̀lú bó ṣe darapọ̀ mọ́ APC- Sheikh Gumi
- Wo ohun tó yẹ kí o ṣe sí ojú abẹ́ rẹ, ''vagina'' lẹ́yìn ìbálòpọ̀
- "Mo fi nǹkan ọkùnrin mi sínú àgádádogo fún ọ̀sẹ̀ méjì fún ìbálòpọ̀, wàhálà bá de"
Ariwo wọn ni iroyin sọ pe o de eti awọn eeyan to wa ni tosi, ti awọn naa wa a wẹ, ti wọn fi sare si wọn.
Ninu fidio kan to wa lori ayelujara ni awọn eero iworan to duro ti wọn ti n gbiyanju lati tu wọn ka.
Ṣugbọn ofo ni igbiyanju wọn.
Bẹẹ naa si ni ololufẹ meji ọhun pariwo ẹ gba wa pẹlu omije loju, eyi to fihan pe wọn n jẹ irora.
"Ao ni i ṣe bẹẹ mọ".
Ti wọn si n tọrọ idariji lọwọ awọn oriṣa, nitori irora to ba wọn.















