Justice for Jubril: Ọwọ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Kebbi tẹ bàbá àti ìyàwó rẹ̀ méjì fún pé wọn so ọmọ pọ̀ mọ́ ewúrẹ́ fún ọdún méjì

Oríṣun àwòrán, KBSTGOV
Ileesẹ ọlọpaa nipinlẹ Kebbi, ti mu ọkunrin kan ati iyawo rẹ meji, fun pe wọn so ọmọ orogún wọn, Jubril Aliyu, ọmọ ọdún mẹwaa, pọ mọ ewurẹ fun ọdun meji.
Ọga Agba Ọlọpaa, DSP Nafiu Abubakar, to fidi iṣẹlẹ naa mulẹ sọ pe awọn ṣi n wadii nkan to mu ki awọn òbí ọmọ naa fi ìyà jẹ ẹ to bẹ ẹ, debi pe wọn ni ko ma a sun pẹlu awọn ewurẹ wọn.
O fi kun un ọrọ rẹ pe ọmọ naa ti n gba itọju nileewosan bayii, ti iwadii si n lọ.
Ẹnikan lára àwọn to n tọ pinpin iṣẹlẹ naa, Amofin Hamza Attahiru, lati ajọ ajafẹtọ ọmọniyan Human Rights Network, sọ pe ẹnikan lára àwọn to doola ẹmi Jubril jẹri pe bi oun ṣe maa n ri ọmọ naa ti wọn so o pọ mọ àwọn ewurẹ jẹ iyalẹnu.
O ni eyi lo mú ki oun si beere lọwọ àwọn iyawo baba rẹ ohun to fa a, o ni wọn fun oun ni esi pe nitori pe ọmọ naa ko gbọ́n daadaa ni.
O ni: "Ibi ti wọn so o mọ pẹlu awọn ewurẹ, ni a ti ba ọmọ naa ninu igbọnsẹ gbígbẹ to jẹ ti ẹ ati ti ewurẹ.
Koda, o ti n jẹ ìgbẹ́ naa.
- Orílẹ̀-èdè Chad pé ọgọ́ta ọdún, àwọn ara ìlú ń pariwo lábẹ́ Aàrẹ Deby tó gba 'Field Marshal'
- Ìyàwó Bukola Saraki fún tìyá-tọmọ olójú búlúù ní N250, 000!
- Ọwọ́ ikọ̀ aláàbò STF tẹ afurasí mẹ́jọ tó lọ́wọ́ nínú ìpànìyàn lemọ́-lemọ́ọ Gúúsù Kaduna
- A ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí lórí ibì tí owó tí àwọn adigunjalẹ̀ gbé ní banki Okeho wọ̀lẹ̀ sí- Ọlọ́pàá
Awọn iyawo baba rẹ sọ pe nitori o ni arun ọpọlọ ati warapa, ni wọn ṣe fi sibẹ."
"O jẹ ibanujẹ ọkàn pe ọmọ naa ti n hu iwa bi ewurẹ, nitori pe o ti pẹ ni aarin wọn."
Sugbọn nínú ifọrọwanilẹnu miran, ọkan lara awọn iyawo baba rẹ sọ pe oun maa n fun un ni oúnjẹ.
Gomina ipinlẹ Kebbi, Abubakar Bagudu ti pàṣẹ pe ki iwadii ijinlẹ waye lori ọrọ Jubril.
Ijọba sọ ninu atẹjade ti wọn fi sita lori iṣẹlẹ naa pe "o ba ni lọkan jẹ pe lati ọdun meji sẹyin ti ìyá ọmọ naa ti kú, ni igbeaye rẹ ti yi pada.
Fidio bi awọn ajafẹtọ ọmọniyan ati awọn ọlọpaa ṣe doola ọmọ naa wa lori ayelujara.
Bakan naa ni Gomina Abubakar Bagudu kede pe ijọba òun ti gbakoso itọju ọmọ naa, eto ilera ati ẹ̀kọ́ rẹ.
- Orílẹ̀-èdè Chad pé ọgọ́ta ọdún, àwọn ara ìlú ń pariwo lábẹ́ Aàrẹ Deby tó gba 'Field Marshal'
- Wo ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa Yahaya Sharif-Aminu tó gba ìdájọ́ ikú ní Kano lórí ẹ̀sùn ọ̀rọ̀ òdì sí Ànọ́bì
- Ẹgbẹ́ òṣèlú ZLP gbàmí tọwọ́tẹsẹ̀ láti díbò gómínà ní Ondo- Agboola Ajayi
- Coronavirus: Ewu wo làwọn òṣìṣẹ́ elétò ìlèra ń kojú ní Nàìjíríà?
- Ifẹ̀họ̀núhàn ń lọ lọ́wọ́ ní Belarus lẹ́yìn tí ìdìbò tùn gbé Ààrẹ̀ Lukashenko tó ti wà nípò fún ọdún 26 wọlé















