Custom: A ti gbẹ́sẹ̀ lé ọjà tí oye rẹ̀ lé ní bílíọ́nù kan náírà lẹ́yìn tí a ti ibodè - ìjọba àpapọ̀

Oríṣun àwòrán, FACEBOOK/NIGERIA CUSTOMS SERVICE
Ajọ aṣọbode Naijiria ni oun ti sẹ ẹdinku si bi wọn ṣe n ko ohun ija wọle sorilẹ-ede yii, lẹyin to gbe agadagodo sẹnu ibode to wọle si Naijiria.
Ọga agba fun ajọ naa, Hameed Ali lo sọ ọrọ yii, nibi ifọrọwerọ kan pẹlu awọn oniroyin lori iṣẹ ti wọn pe ni "Ex-Swift Response" ni Abuja.
O ni ajọ ọhun ti gbẹsẹ le kiko ohunkohun wọle si orilẹ-ede yii ni gbogbo ẹnu ibode ilẹ to wọle si Naijiria.
- Taló ya fídíò ibi tí Aisha Buhari ti ń bínú ní Aso Rock?
- Ọlọ́pàá ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí láti mọ òkodoro bí wọ́n ṣe gbé ọmọ tuntun náà sin láàyè ní India
- Ìdùnnú ni yóò jẹ fún wa ti wọn bá ṣe àwọn ọnà tí kò dára wọnyíì- Bosun Aguda
- Ajọ Amnesty International ní kò dín ní 119 ọmọ Nàìjíríà ti wọ́n ti gba ìdájọ́ ikú ní Malaysia
Ajọ naa ni wọn ti awọn ibode ọhun lati oṣu kẹjọ, ọdun 2019 latari ati lee jẹ ki ọrọ aje orilẹ-ede yii dagba sii.
Ni eyi to si ti n bi eso rere ti gbogbo oju le ri ka ninu okowo ati eto aabo Naijiria.
Ali fikun un pe, awọn ibode naa di titi latari ati lee dẹkun bi awọn kan ṣe n ko ọja wọle sorilẹ-ede yii lọna ti ko tọ.
O ni bayii, ọna to yẹ ni ẹnikẹni to ba fẹ ko ọja wọ Naijiria gbọdọ gba koo wọle ki o si pa owo ori fun Naijiria.
Hammed ni ọja ti wọn ti gbẹsẹ le lati igba ti wọn ti ti ibode Naijiria ni iye rẹ le ni biliọnu kan ati irinwo, ti ajọ ọhun si ti n pa owo ti ko din ni biliọnu marun un naira wọle sapo ijọba lojoojumọ Ilééṣẹ́ Aṣọ́bodè Naijiria n pa bílíọ̀nù N5.8 wọlé lójúmọ́ lẹ́yìn tíjọba ti ẹnu bodè -Ali.
O ṣalaye pe awọn eeyan Naijiria ni ẹtọ labẹ ofin lati rinrin ajo lọ sibikibi, ṣugbọn wọn ko fi aaye gba ẹnikẹni lati ko ohunkohun wọle si Naijiria lai gba aṣẹ.
Ọga aṣọbode ọhun ni ajọ naa ko ṣetan lati ṣi ẹnu ibode to wọle si orilẹ-ede yii.
O ni titi di igba ti awọn orilẹ-ede to yi Naijiria ka yoo fi tẹle ilana ti ajọ ECOWAS gbe kalẹ lori owo ṣiṣe lati orilẹ-ede kan si omiran.
Hammed pari ọrọ rẹ pe lati igba ti ajọ naa ti gbe kọkọrọ si ẹnu ibode, ọrọ aabo ti ṣẹnu ire ju ti tẹlẹ lọ.
- Olùkọ́ àgbà tó fipá bá ọmọ ọdún 13 lò yóò fojú ba ilé ẹjọ́ ni Benue
- Uganda ti bẹrẹ ìgbésè láti fi ikú ṣefàjẹ fún ẹní bá ṣe ìgbéyàwó akọ si akọ ati abo si abo
- Èmi kò sí nílé, ọkọ́ mi ló leè sọ bóyá lóòtọ́ọ́ ló fẹ́ gbéyàwó àbí bẹ́ẹ̀ kọ́ - Aisha fèsì
- Àbà ètò ìṣúná 2020 tó kéré yóò mú kí ètò ààbò mẹ́hẹ síi ní Nàìjíríà-Onwoye
















