Seyi Makinde: Èmi àti àwọn èèyàn Ọyọ yóò máa fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú àwọn ológun

Oríṣun àwòrán, Makinde/Twitter
Gómìnà ìpínlẹ̀ Oyo, Seyi Makinde ti fí èrò ọkan rẹ̀ han pé, ìjọba oun àti àwọn ènìyàn ìpínlẹ̀ Oyo yóò tẹ̀síwájú láti maa fọ́wọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ilé iṣẹ́ ọmọogun Nàìjíríà.
Makinde sọ ọ̀rọ̀ yìí lásìkò tó péju síbi ayẹyẹ ìsíde idije ibọn yinyin laarin awọn ipẹẹrẹ ologun (NASAC), eyi to wáye ni ileesẹ ọwọ keji ologun ti Adekunle Fajuyi to wa ladugbo Odogbo, Ọjọọ, nilu Ibadan.

Oríṣun àwòrán, Seyi Makinde
Makinde ní ìnú òun dún fun àyẹsí ti wọ́n fún oun, to si jẹjẹ pe oun ati awọn eeyan ipinlẹ Ọyọ yoo tubọ maa fọwọsowọpọ pẹlu awọn osisẹ ologun.
" Mo gbadúrà pé gbogbo àwọn akopa nínú ètò náà ni yoo se àṣeyọri, ti eto naa yoo si jẹ mánigbàgbé fun wọn ní ìpínlẹ̀ Oyo."








