Sunday Igboho latest news: Àwa àgbààgbà Yorùbá kò fi ọwọ́ sí ìdásìlẹ̀ Oduduwa Nation - YCE

Akọwe fun ẹgbẹ awọn agbaagba ilẹ Yoruba, Dokita Kunle Olajide ti sọ pe awọn ko fi ara mọ ijijagbara fun orilẹ-ede Oduduwa, to n waye.

Ninu ifọrọwanilẹnuwo pẹlu BBC, o ni ẹya Yoruba ti jiya pupọ fun orilẹ-ede Naijiria, paapaa lori ọrọ ominira kuro lọwọ amunisin, ati lẹyin to gba ominira tan.

Lẹyin naa lo tun tọka si ipa ti Yoruba ko ninu ogun abẹle Biafra to waye.

O ni Yoruba ni igbagbọ pe orilẹ-ede Naijiria ṣi ma a dara laipẹ

O ni lootọ ni nkan ko lọ bo ṣe yẹ ko lọ, paapaa lati bi ọdun marun ti ijọba to wa nibẹ bayii ti gun ori aleefa.

"Lati igba ti mo ti de aye, ko si asiko ti ija ẹlẹyamẹya ati ẹsin pọ ni Naijiria buru to bo ṣe ri bayi. Bakan naa ni ọrọ abo.

"O fojuhan pe ijọba naa fi si apa kan."

O tẹsiwaju ninu ọrọ rẹ pe awọn ko ti i ṣetan lati lọ si ibi kankan, pe ko rọrun bẹẹ, "nitori pe a ti wa papọ, o ti le ni ọgọrun ọdun".

O ni ṣaaju ki awọn oyinbo to de ni ibaṣepọ ti wa laarin awọn ẹya to parapọ di Naijiria.

"Awọn ọdọ to n binu ni ẹtọ lati binu, nitori pe wọn n ja fun ọjọ ọla wọn ni.

Ṣugbọn awa agbagba n sọ pe ko yẹ ki wọn tẹ ẹ jẹjẹ, nitori pe ọmọ ọdọ naa ma an fi ọgbọn ṣe."

"A ni ki wọn o rọra, nitori pe a ko ni i fẹ ki ogun abẹle kankan ti ọdọ Yoruba bẹrẹ.

O ni ayafi to ba jẹ pe aarẹ deedee sọrọ lọjọ kan pe ki kaluku ma a ba tiẹ lọ.

"Awa naa ṣetan. ṣugbọn kii ṣe ki a doju ija kọ ijọba Naijiria nitori pe kaakiri Naijiria ni awọn ọmọ Yoruba wa.

Ka fi suuru yanju rẹ ni awa agbaagba n sọ."