Ooni Ogunwusi: Ìròyìn òfégè ló ń lọ kiri pé ìyàwó mí bimọ tuntun

Lẹnu ọjọ mẹta yii ni iroyin tan kalẹ pe olori ni aafin Ile Ife, Naomi Silekunola Ogunwusi ti bimọ ọkunrin lanti-lanti fun Kabiyesi Ọọ́ni Adeyeye Ogunwusi.

Gbogbo eti to si gbọ̀ iroyin naa lo n fo fayọ, ti wọn si n ki ọba alaye naa pe wọn ku oriire ayọ ọmọ tuntun.

Amọ niwọn igba to jẹ pe BBC Yoruba kii bawọn he eera ti ko ni ọmọ ninu, idi ree ta fi kan si aafin Ọọni lati wadi iroyin naa, ka si fi idi otitọ mulẹ nipa isẹlẹ yii.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Amọ abọ iwadi wa ni pe ofuutu fẹẹtẹ, aasa ti ko ni ọmọ ninu gbaa ni iroyin naa, nitori Olori Naomi ko bi ọmọ tuntun.

Bẹẹ si ni Ọọni Ile Ifẹ, Ọba Adeyẹye Ẹnitan Ogunwusi ti sọ pe, ko si ootọ kankan ninu iroyin to gbode naa pe iyawo oun bimọ.

Nigba to n fidi otitọ ọrọ yii mulẹ fun BBC Yoruba, Agbẹnusọ fun Ọọni, Moses Olafare sọ pe irọ nla ni ahesọ ọrọ naa.

O ni awọn ko kede fun ẹnikankan pe iyawo Ọọni bimọ nitori naa, iroyin ayederu gba a ni ọrọ naa jẹ.

Kaakiri oju opo ayelujara ni iroyin yii ti gbode, ti awọn eeyan kan si ti n fi ọrọ ikini ranṣẹ si Ọọni ati iyawo rẹ, Olori Naomi Silekunola Ogunwusi.

Nibi ti ọrọ yii gbalẹ de, awọn kan ni ọmọ ọkunrin ni ọmọ naa.

Ninu ọrọ ti Olafare sọ, o ni ki awọn to ba n ṣiṣẹ akọroyin ri pe, wọn tẹle ilana iwadii ọfintoto, ki wọn to gbe iroyin jade.

A ko ridi ọrọ fi mulẹ ibi ti iroyin yii ti kọkọ jẹ yọ, ṣugbọn o bẹrẹ lẹnu igba ti awọn eeyan ko ri Olori Naomi nita lasiko ọdun Ọlọjọ to waye.

Eyi lo mu ki awọn kan maa sọ pe, o ṣeeṣe ki iyawo Ọọni ti bimọ ni ṣugbọn nibayii, aafin ti tako iroyin naa.