A ó ṣe ìwádìí ẹ̀dà àrùn Covid-19 tuntun ní ìpínlẹ̀ mẹ́rin – NCDC

Oríṣun àwòrán, @Nairametrics
Ajọ to n gbogun ti ajakalẹ arun ni Naijiria, NCDC, ti kede pe ohun ti n ṣe iwadii ẹda arun Covid-19 tuntun, EG.5 ati BA.2.86.
Ninu atẹjade kan to fi lede lọjọ Abamẹta, ajọ ọhun sọ pe igbimọ to n ri si ọrọ arun naa ko dakẹ lati maa tọpipin rẹ lagbaye.
O ni “Igbimọ wa to n ṣe ọfintoto arun n tẹsiwaju lati maa fun wa ni iroyin nipa rẹ ati bo ṣe n ṣọṣẹ lara eeyan.”
“Lootọ ni pe ẹda tuntun yii ko tii tan kalẹ ṣugbọn a n tẹsiwaju lati maa ṣe iwadii nipa rẹ, bẹẹ la tun rọ awọn oṣiṣẹ to n ṣe ayẹwo arun naa lati maa fi esi ayẹwo awọn to ni arun ọhun ṣọwọ si laabu NCDC fun ayẹwo kikun.”
“NCDC atawọn alabaṣiṣẹpọ rẹ n ṣiṣẹ takuntakun lati ri pe a gbe ibi ti wọn ti le ṣayẹwo ẹda tuntun naa kalẹ ni ipinlẹ mẹrin ki a le ni ẹkunrẹrẹ imọ nipa bo ṣe n tan kalẹ lawọn ipinlẹ.”
“Bakan naa, a tun ti n pin awọn ohun elo ti wọn fi n ṣayẹwo arun Covid-19 ni kankan kaakiri lati le jawe sobi bi a ṣe n ṣe ayẹwo rẹ.”
O fi kun pe ọna ati dena arun naa ko yipada si bo ṣe wa tẹlẹ eyii to jẹ fifọ ọwọ ẹni loorekoore, ṣiṣe ayẹwo arun ọhun ati lilo ibomu nibi ti ọpọ ero ba wa.
Atẹjade NCDC sọ siwaju awọn araalu ko nilo lati maa ko aya soke nitori iroyin ẹda arun naa tuntun yii.
O ni “gẹgẹ bi a ṣe maa n sọ tẹlẹ Covid-19 ko le tan nilẹ, amọ iṣoro to wa nibẹ ni awọn ti arun naa lewu fun julọ.”
“Awọn to wa ninu ewu arun naa julọ ko kọja awọn arugbo, awọn ti arun kan tabi omiran ti n ba finra tẹlẹ bii ẹjẹ riru, itọ ṣuga atawọn to n gba itọju arun jẹjẹrẹ lọwọ...”












